world-service-rss

BBC News Yorùbá

Àwọn ohun tó yẹ kí o mọ̀ nípa Robert Prevost Leo XIV, Póòpù tuntun fún ìjọ Kátólíìkì

Àwọn ohun tó yẹ kí o mọ̀ nípa Robert Prevost Leo XIV, Póòpù tuntun fún ìjọ Kátólíìkì

Ọjọ́bọ, 8 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 19:52:16

Robert Prevost ni Popu akọkọ lati orilẹede Amẹrika, bi o tilẹ jẹ wi pe ọpọlọpọ eeyan lo tun n fi oju ara ilẹ Larin Amerika wo o.

“Kí àlááfíà wà pẹ̀lú yín” Pope tuntun, Leo XIV bá àgbáyé sọ̀rọ̀ fún ìgbà àkọ́kọ́

"Kí àlááfíà wà pẹ̀lú yín" Pope tuntun,  Leo XIV bá àgbáyé sọ̀rọ̀ fún ìgbà àkọ́kọ́

Ọjọ́bọ, 8 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 18:17:18

Lọjọbọ ni wọn kede orukọ Robert Prevost gẹgẹ niẹni ti yoo maa dari ijọ naa lẹyin ipapoda Popoe Francis.

Joe Biden korò ojú pé Donald Trump ń sọ̀rọ̀ ṣàkàṣàkà, kò sọ̀rọ̀ bíi Ààrẹ Amẹ́ríkà

Joe Biden korò ojú pé Donald Trump ń sọ̀rọ̀ ṣàkàṣàkà, kò sọ̀rọ̀ bíi Ààrẹ Amẹ́ríkà

Ọjọ́bọ, 8 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 13:10:17

Aarẹ Amẹrika ana naa sọrọ lori erongba rẹ nipa Aarẹ Donald Trump to wa lori alefa lọwọ.

“Lẹ́yìn tí Ajínigbé gba N14m owó ìtúsílẹ̀, àpò ìrẹsì, adìẹ méjìlá tí wọn dín gbẹ, ohun mímu 24, káàdì ìpè N10,000, wọ́n tún ń bèèrè N70m míì”

"Lẹ́yìn tí Ajínigbé gba N14m owó ìtúsílẹ̀, àpò ìrẹsì, adìẹ méjìlá tí wọn dín gbẹ, ohun mímu 24, káàdì ìpè N10,000, wọ́n tún ń bèèrè N70m míì"

Ọjọ́bọ, 8 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 12:47:23

BBC Yorùbá kàn sí méjì nínú àwọn ẹbí àwọn èèyàn méje tí wọn jí gbé náà, tí wọn sì ṣàlàyé bí aáyan wọn láti gba ìdásílẹ̀ àwọn èèyàn wọn lọ́wọ́ ajínigbéc, ṣe já sí pàbó.

Kò ṣe é má gbọ̀ ọ́

Kò ṣe é má gbọ̀ ọ́

Ọjọ́bọ, 8 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 12:44:48

Àkójọpọ̀ ìròyìn káàkiri Nàìjíríà tí kò ṣe é má gbọ̀ ọ́

Ètò yíyan Póòpù tuntun ń tẹ̀síwájú bí èéfí dúdú ṣe jáde láti Sistine Chapel

Ètò yíyan Póòpù tuntun ń tẹ̀síwájú bí èéfí dúdú ṣe jáde láti Sistine Chapel

Ọjọ́rú, 7 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 08:34:46

Èéfín dúdú ló jáde lálẹ́ àná ní Sinistine Chapel tí ètò ìdìbò náà ti ń wáyé, tí èyí sì túmọ̀ sí pé àwọn cardinal náà kò ì fẹnukò lórí ẹni tó máa di póòpù tuntun.

Àlàyé rèé lórí ìdí tí aáwọ̀ ẹgbẹ́ òṣèlú Labour ṣe ń le koko sí, bí igun Abure àti Usman se dojú ogun kọ ara wọn

Àlàyé rèé lórí ìdí tí aáwọ̀ ẹgbẹ́ òṣèlú Labour ṣe ń le koko sí, bí igun Abure àti Usman se dojú ogun kọ ara wọn

Ọjọ́bọ, 8 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 11:03:54

Ikọ̀ ti Usman, tí Alex Otti àti Peter Obi faramọ́, ti fún Abure ní ọjọ́ méjì láti yé pe ara rẹ̀ ní alága ẹgbẹ́ òṣèlú Labour Party mọ́ nítorí sáà rẹ̀ ti parí.

Fídíò rèé nípa bí wọn ṣe máa ń yan Póòpù tuntun

Fídíò rèé nípa bí wọn ṣe máa ń yan Póòpù tuntun

Ọjọ́bọ, 8 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 06:54:17

Ipade ti wọn maa n ṣe lati yan olori ijọ Aguda tuntun naa lo n waye lẹyin isin Novemdiales, eyi ti wọn ṣe lati tọrọ isinmi ayeraye fun Poopu Francis to di oloogbe.

Ìdí rèé tí Bàálù Herbert Wigwe fi já ní Amẹ́ríkà èyí tó rán òun, aya àti ọmọ rẹ̀ sọ́run lójijì

Ìdí rèé tí Bàálù Herbert Wigwe fi já ní Amẹ́ríkà èyí tó rán òun, aya àti ọmọ rẹ̀ sọ́run lójijì

Ọjọ́bọ, 8 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 10:07:09

Abajade nipa ohun to fa a ti baalu to gbe Herbert Wigwe ati ẹbi rẹ fi ja, lo wa ninu atẹjade abọ iwadii ti ajọ to n se akoso eto irina ni Amẹrika gbe jade.

Ṣé lóòótọ́ ni Nnamdi Kanu pàṣẹ kí wọn máà pa àwọn ọlọ́pàá, tún lérí láti kọlu ìpínlẹ̀ Eko?

Ṣé lóòótọ́ ni Nnamdi Kanu pàṣẹ kí wọn máà pa àwọn ọlọ́pàá, tún lérí láti kọlu ìpínlẹ̀ Eko?

Ọjọ́bọ, 8 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 09:40:46

Ẹlẹrii yii jẹ oṣiṣẹ DSS. Ọkunrin naa fi awọn ẹri to n kede ibi ti Kanu ti n fun awọn kan laṣẹ lati ba Naijiria ja, han.

Ìyàwó gun ọkọ lọ́bẹ pa lẹ̀yìn ọjọ́ kẹsàn-án ìgbeyàwó

Ìyàwó gun ọkọ lọ́bẹ pa lẹ̀yìn ọjọ́ kẹsàn-án ìgbeyàwó

Ọjọ́bọ, 8 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 08:42:56

Agbẹnusọ ileeṣẹ ọlọpaa Kano, SP Abdullahi Haruna Kiyawa ni iṣẹlẹ naa waye ni agbegbe Faraw ni ijọba Tarauni nipinlẹ Kano.

Wo ìgbésẹ̀ tí o le è gbé láti mọ̀ bóyá ojúlówó ni nọ̀ńbà NIN rẹ àti ànfàní lílo rẹ̀

Wo ìgbésẹ̀ tí o le è gbé láti mọ̀ bóyá ojúlówó ni nọ̀ńbà NIN rẹ àti ànfàní lílo rẹ̀

Ọjọ́rú, 7 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 11:01:03

Agbẹnus fun ajọ NIMC ni idasilẹ oju opo NIN Auth yoo pese aabo fun awọn iroyin nipa araalu, ti ọpọ ẹka ijọba yoo si jẹ anfani rẹ.

Àlàyé rèé lórí ìdí tí Póòpù fi máa ń wọ bàtà pupa àti ìdáhùn àwọn ìbéèrè míràn tó rú ọ lójú

Àlàyé rèé lórí ìdí tí Póòpù fi máa ń wọ bàtà pupa àti ìdáhùn àwọn ìbéèrè míràn tó rú ọ lójú

Ọjọ́bọ, 8 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 05:36:45

Ọpọ eeyan lo ti n foju sọna si ibo ni agbaye ti Pope tuntun yoo ti wa.

Bí ìgbẹ́jọ́ Alfa Abdulrahman tí wọn fẹ̀sùn ìfipábánilòpọ̀ àti ikú Afsot Yetunde kàn ní Ilorin ṣe lọ lónìí rèé, bí bàbá olóògbé ṣe bú sẹ́kún

Bí ìgbẹ́jọ́ Alfa Abdulrahman tí wọn fẹ̀sùn ìfipábánilòpọ̀ àti ikú Afsot Yetunde kàn ní Ilorin ṣe lọ lónìí rèé, bí bàbá olóògbé ṣe bú sẹ́kún

Ọjọ́rú, 7 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 12:45:37

Awọn olujẹjọ maraarun ti wọn fi ẹsun ipaniyan naa kan, to fi mọ Alfa Abdulrahman, ni wọn farahan ni ile ẹjọ naa.

Ètò yíyan Póòpù tuntun ń tẹ̀síwájú bí èéfí dúdú ṣe jáde láti Sistine Chapel

Ètò yíyan Póòpù tuntun ń tẹ̀síwájú bí èéfí dúdú ṣe jáde láti Sistine Chapel

Ọjọ́rú, 7 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 08:34:46

Èéfín dúdú ló jáde lálẹ́ àná ní Sinistine Chapel tí ètò ìdìbò náà ti ń wáyé, tí èyí sì túmọ̀ sí pé àwọn cardinal náà kò ì fẹnukò lórí ẹni tó máa di póòpù tuntun.

Kí ló ń jẹ́ “Shadow Government”, tí Pat Utomi gbé kalẹ̀ láti tako ìjọba Tinubu?

Kí ló ń jẹ́ "Shadow Government", tí Pat Utomi gbé kalẹ̀ láti tako ìjọba Tinubu?

Ọjọ́rú, 7 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 11:35:15

Pat Utomi sọ pé àwọn ṣàgbékalẹ̀ ìjọba òdìkejì náà tó pe orúkọ rẹ̀ ní “Big Tent Coalition Shadow Government” lórí ayélujára.

Baálẹ̀ Yemi Ogunyemi, Baálẹ̀ Oluyole àti àgbà ọ̀jẹ̀ agbóhùnsáfẹ́fẹ́, jáde láyé

Baálẹ̀ Yemi Ogunyemi, Baálẹ̀ Oluyole àti àgbà ọ̀jẹ̀ agbóhùnsáfẹ́fẹ́, jáde láyé

Ọjọ́rú, 7 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 10:12:40

Ọkan lara awọn ọmọ Oloogbe, DSP Wale Ogunyẹmi ṣe alaye fun BBC Yoruba pe lati bii oṣu meloo kan sẹyin ni Oloye Ogunyẹmi ti n ṣe aisan.

Boko Haram ti gboró, bàálù Drone ló ń lò láti kọlu aráàlú ní Borno - Aṣojú-ṣòfin

Boko Haram ti gboró, bàálù Drone ló ń lò láti kọlu aráàlú ní Borno - Aṣojú-ṣòfin

Ọjọ́rú, 7 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 09:20:19

Jaha ni awọn ohun ija to wa lọwọ awọn agbebọn Boko Haram ju eyi to wa lọwọ awọn ọmọ Ologun Naijiria lọ.

Nínú ọba 82, ìjọba kéde ojúlówó ọba 16 péré ní ilẹ̀ Benin, ariwo sọ

Nínú ọba 82, ìjọba kéde ojúlówó ọba 16 péré ní ilẹ̀ Benin, ariwo sọ

Ọjọ́rú, 7 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 07:10:18

BBC Yorùbá lọ sílẹ̀ Benin láti mọ ìdí tí ìjọba ilẹ̀ náà ṣe kéde ojúlówó ọba mẹ́rìndínlógún péré nínú ọba méjìlélọ́gọ́rin àti ìhà táwọn ọba wọn gba adé lórí wọn kọ sí ìṣẹ̀lẹ̀ náà.

Ìdí rèé tí mo ṣe lọ sọ́dọ̀ àjọ EFCC - Iyabo Ojo

Ìdí rèé tí mo ṣe lọ sọ́dọ̀ àjọ EFCC - Iyabo Ojo

Ọjọ́rú, 7 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 05:26:23

Iyabo Ojo salaye pe ilẹ Gẹẹsi loun wa, ti EFCC fi ke si oun amọ ọjọ karun un, oṣu Karun un yii gan ni oun to yọju si EFCC nigba ti oun pada de si Naijiria.

Darapọ̀ mọ́ wa lórí WhatsApp

Darapọ̀ mọ́ wa lórí WhatsApp

Ọjọ́ Ajé, 15 Oṣù Ìgbé 2024 ní 11:20:59

Má jẹ́ kí etí rẹ ó di sí gbogbo ìròyìn ohun tó ń lọ ní Naijiria àti káàkiri àgbáyé. Mọ̀ nípa wọn lórí ìkànnì Whatsapp rẹ

Àlàyé rèé lórí ìdí tí ọ̀pọ̀ akẹ́kọ̀ọ́ ṣe fìdí rẹmi nínú ìdánwò UTME, bí JAMB ṣe kéde èsì ìdánwò náà

Àlàyé rèé lórí ìdí tí ọ̀pọ̀ akẹ́kọ̀ọ́ ṣe fìdí rẹmi nínú ìdánwò UTME, bí JAMB ṣe kéde èsì ìdánwò náà

Ọjọ́ Ìsẹ́gun, 6 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 08:45:39

Gẹ́gẹ́ bí JAMB ṣe sọ, nínú èèyàn 1,955,069 tó ṣe ìdánwò náà, àwọn tó lé ní ìlàjì ni kò gba tó máàkì 200.

Wo ìgbeyàwó ọ̀pọ̀ èèyàn tó wáyé ní ṣọ́ọ̀ṣì kan níbi tí ọkùnrin ti ń fẹ́ ju ìyàwó kan lọ

Wo ìgbeyàwó ọ̀pọ̀ èèyàn tó wáyé ní ṣọ́ọ̀ṣì kan níbi tí ọkùnrin ti ń fẹ́ ju ìyàwó kan lọ

Ọjọ́ Ìsẹ́gun, 6 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 05:46:01

Igba mẹta ni iru igbeyawo yii maa n waye lọdun nile ijọsin yii lasiko ọdun Ajinde, ninu oṣu Kẹsan an ati oṣu Kejila.

Kà nípa àìsàn tó lè pa ọmọ ìkókó

Kà nípa àìsàn tó lè pa ọmọ ìkókó

Ọjọ́ Ìsẹ́gun, 6 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 09:10:51

Awọn aisan miran wa ti ko ni Ie pa ọmọ ikoko, ṣugbọn ko ni Ie jẹ ki wọn dagba, rin tabi sọrọ.

Ooni ṣe pàtàkì fún ìṣọ̀kan àti ìlọsíwájú Naijiria – Goodluck Jonathan

Ooni ṣe pàtàkì fún ìṣọ̀kan àti ìlọsíwájú Naijiria – Goodluck Jonathan

Ọjọ́ Ajé, 5 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 16:12:14

Jonathan lo sọ ọrọ naa ni ilu bibi rẹ, Otuoke, to wa nipinlẹ Bayelsa.

Kí ló ń fa àṣìṣe lórí ètò ẹ̀yáwó akẹ́kọ̀ọ́, táwọn akẹ́kọ̀ọ́jáde fi ń rí ẹ̀yáwó náà gba?

Kí ló ń fa àṣìṣe lórí ètò ẹ̀yáwó akẹ́kọ̀ọ́, táwọn akẹ́kọ̀ọ́jáde fi ń rí ẹ̀yáwó náà gba?

Ọjọ́ Ajé, 5 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 09:44:08

Àwọn akẹ́kọ̀ọ́ náà ní lẹ́yìn tí àwọn ti parí ètò ẹ̀kọ́ àwọn ni àjọ tó ń rí sí ẹ̀yáwó fáwọn akẹ́kọ̀ọ́, Nigeria Education Loan Fund, NELFUND ṣẹ̀ṣẹ̀ ń san owó fáwọn ilé ẹ̀kọ́ àwọn.

Ọlọ́pàá ṣàwárí obìnrin tó sọnù láti ọdún 1962

Ọlọ́pàá ṣàwárí obìnrin tó sọnù láti ọdún 1962

Ọjọ́ Ajé, 5 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 05:29:31

Ẹni ogun ọdun ni Audrey Backeberg nigba to kuro nile niluu Reedsburg lọjọ keje, oṣu Keje, ọdun 1962.

Àlàyé lórí ìdí tí Ààrẹ Togo fi lè wà nípò títí láí

Àlàyé lórí ìdí tí Ààrẹ Togo fi lè wà nípò títí láí

Ọjọ́ Àìkú, 4 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 15:05:50

Awọn ọmọ ẹgbẹ alatako orilẹede naa ti sọ pe igbesẹ ọhun ko ṣẹyin akitiyan ijọba lati ri daju pe Gnassingbé ko fi ipo silẹ lailai.

Wo àwọn nǹkan tó yẹ láti ṣe tí o bá fẹ́ máa lo ẹ̀rọ a-mú-oúnjẹ-gbóná

Wo àwọn nǹkan tó yẹ láti ṣe tí o bá fẹ́ máa lo ẹ̀rọ a-mú-oúnjẹ-gbóná

Ọjọ́ Àìkú, 4 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 10:14:56

Gbígbé oúnjẹ sínú ẹ̀rọ a-mú-oúnjẹ-gbóná (microwave) ní àwọn ipa kan tó máa ń ní lórí ìlera èèyàn pàápàá látara àwọn oúnjẹ tí èèyàn ń gbé sínú ẹ̀rọ yìí.

‘Wọ́n sọ fún ìyá mi láti jù mí nù ní kékeré nítorí mo ní àìsàn ‘Sickle Cell’ àmọ́ mo tí pé ọdún 65 báyìí’

'Wọ́n sọ fún ìyá mi láti jù mí nù ní kékeré nítorí mo ní àìsàn 'Sickle Cell' àmọ́ mo tí pé ọdún 65 báyìí'

Ọjọ́ Àìkú, 4 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 12:03:56

Abílékọ Modupe Olopade Popoola ṣàlàyé àwọn ìlàkàkà tó dojúkọ gẹ́gẹ́ bí ẹni tó ní àìsàn Sickle Cell nígbà tó ń dàgbà.

Ọlọ́pàá bá òkú ọmọ Nàìjíríà tí wọ́n gún pa sínú ilé ní ó ku ọ̀sẹ̀ méjì tó máa parí ìkẹ́kọ̀ọ́ nọ́ọ̀sì ní US

Ọlọ́pàá bá òkú ọmọ Nàìjíríà tí wọ́n gún pa sínú ilé ní ó ku ọ̀sẹ̀ méjì tó máa parí ìkẹ́kọ̀ọ́ nọ́ọ̀sì ní US

Ọjọ́ Àìkú, 4 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 07:39:53

Ọjọ́ Kẹrìndínlọ́gbọ̀n, oṣù Kẹrin ni wọ́n bá òkú Tamilore nínú yàrá rẹ̀ nígbà tí àwọn ọlọ́pàá já ilẹ̀kùn àbáwọlé rẹ̀.

Ìjọ Àgùdà korò ojú sí Trump lórí àwòrán ara à rẹ̀ bíi Póòpù tó gbé síta

Ìjọ Àgùdà korò ojú sí Trump lórí àwòrán ara à rẹ̀ bíi Póòpù tó gbé síta

Ọjọ́ Àìkú, 4 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 09:15:43

Aworan jade ni ọjọ diẹ sẹyin ti Trump kede pe o wu oun lati di Pope.

Darandaran tó fi mààlúù jẹko l’Ondo gba ìdájọ́ ẹ̀wọ̀n ọdún mẹ́wàá

Darandaran tó fi mààlúù jẹko l'Ondo gba ìdájọ́ ẹ̀wọ̀n ọdún mẹ́wàá

Ọjọ́ Àbámẹ́ta, 3 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 13:53:30

Ire oko to to miliọnu lọna aadọta naira (50m) ni wọn lo bajẹ.

Kókó mẹ́wàá tó yẹ kí o mọ nípa àìsàn Sémìí-sémìí (Asthma) réè

Kókó mẹ́wàá tó yẹ kí o mọ nípa àìsàn Sémìí-sémìí (Asthma) réè

Ọjọ́bọ, 23 Oṣù Bélú 2023 ní 10:30:33

Asthma le jẹ aisan to lagbara lootọ ṣugbọn pẹlu itọju to peye, eeyan le gbe igbe aye alaafia pẹlu rẹ.

Wo àwọn ọmọ Naijiria mẹ́fà tí ile-ẹjọ́ ti dájọ́ ikú fún

Wo àwọn ọmọ Naijiria mẹ́fà tí ile-ẹjọ́ ti dájọ́ ikú fún

Ọjọ́ Ìsẹ́gun, 6 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 06:16:17

Lẹyin ti kootu ba ti dajọ iku fun eeyan tan, ohun to ku ni ki gomina ipinlẹ naa buwọ lu iwe idajọ iku naa.

185,000 ọmọ ogun Russia ló ti bá ogun lọ ní Ukraine

185,000 ọmọ ogun Russia ló ti bá ogun lọ ní Ukraine

Ọjọ́ Ajé, 5 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 17:29:53

Eeyan 45,287 ni Russia padanu sinu ogun naa lọdun ọhun nikan ṣoṣo.

Ìdí rèé tí Ọlọ́pàá àti Amotekun ṣe kọjú ìjà síra wọn l’Ondo, tí ọ̀pọ̀ èèyàn sì farapa

Ìdí rèé tí Ọlọ́pàá àti Amotekun ṣe kọjú ìjà síra wọn l'Ondo, tí ọ̀pọ̀ èèyàn sì farapa

Ọjọ́ Ajé, 5 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 10:34:49

Agbẹnusọ fun ileesẹ ọlọpaa ni ipinlẹ Ondo ṣalaye ni awọn ọlọpaa lo kọkọ de ibi ti iṣẹlẹ naa ti waye, kawọn Amotekun to de bii ologun lori ọkada.

Lẹ́yìn ò rẹyìn, EFCC ṣàlàyé ìdí tí VDM fi wà ní àhámọ́ rẹ̀

Lẹ́yìn ò rẹyìn, EFCC ṣàlàyé ìdí tí VDM fi wà ní àhámọ́ rẹ̀

Ọjọ́ Ajé, 5 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 11:10:33

Dele Oyewale sọ fún BBC lọ́jọ́ Ajé pé àwọn kan ló kọ̀wé ẹ̀sùn tako VDM ránṣẹ́ sí àwọn láwọn fi nawọ́ gán an.

Ìyàwó ilé méjì dèrò ẹ̀wọ̀n fún fífi PoS ta owó náírà tó tó N3.8m àti N1.6m

Ìyàwó ilé méjì dèrò ẹ̀wọ̀n fún fífi PoS ta owó náírà tó tó N3.8m àti N1.6m

Ọjọ́ Ajé, 5 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 08:53:54

Gẹgẹ bi ajọ EFCC to n gbogun ti iwa ibajẹ ati fifi abuku kan naira ṣe ṣalaye, iwa to lodi sofin Banki apapọ Naijiria ni lati maa ta owo naira.

Ìná tún sọ ní Ibadan, ọ̀pọ̀ dúkìá tún báa lọ

Ìná tún sọ ní Ibadan, ọ̀pọ̀ dúkìá tún báa lọ

Ọjọ́ Àbámẹ́ta, 3 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 08:10:41

Idaji Ọjọ Ẹti ni ijamba ina naa ṣẹlẹ

A ò bá ohun ìgbéṣùmọ̀mí lára Nnamdi Kanu -Ẹlẹ́rìí tí DSS pè

A ò bá ohun ìgbéṣùmọ̀mí lára Nnamdi Kanu -Ẹlẹ́rìí tí DSS pè

Ọjọ́ Àbámẹ́ta, 3 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 10:35:22

Olùjẹ́rìí kan tó pé ara à rẹ ní AAA sọ èyí nígbà tó ń dáhùn ìbéèrè lọ́wọ́ agbẹjọ́rò Nnamdi Kanu, Kanu Agabi.

A ò gbà pé ìdájọ́ òdodo ti wáyé lórí ikú Bamise tí awakọ̀ BRT pa - Ẹbí Bamise Ayanwola fárígá lẹ́yìn ìdájọ́

A ò gbà pé ìdájọ́ òdodo ti wáyé lórí ikú Bamise tí awakọ̀ BRT pa - Ẹbí Bamise Ayanwola fárígá lẹ́yìn ìdájọ́

Ọjọ́ Àbámẹ́ta, 3 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 09:47:23

Gẹgẹ bi igbimọ olupẹjọ ti ṣalaye, ni nnkan bi ago meje alẹ ni wọn fipa ba Bamise lopọ ti wọn si tun ṣeku pa a lopopona Lekki-Ajah ati afara Carter Bridge.

Èmi ni Ọba Fuji, kí Kwam 1 má pe ara rẹ̀ bẹ́ẹ̀ mọ́ – Kollington Ayinla

Èmi ni Ọba Fuji, kí Kwam 1 má pe ara rẹ̀ bẹ́ẹ̀ mọ́ – Kollington Ayinla

Ọjọ́ Àbámẹ́ta, 3 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 17:37:59

Ọrọ naa lo jẹyọ latari ọrọ to n lọ nipa ibaṣepọ rẹ pẹlu Wasiu Ayinde Marshal, ti ọpọ mọ si K1 De Ultimate.

Ìjọba Saudi Arabia kéde ìjìyà tuntun fún àwọn tó ń wọ ilẹ̀ náà lọ́nà àìtọ́

Ìjọba Saudi Arabia kéde ìjìyà tuntun fún àwọn tó ń wọ ilẹ̀ náà lọ́nà àìtọ́

Ọjọ́ Àbámẹ́ta, 3 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 16:12:47

Gẹgẹ bi ẹka naa ṣe ṣalaye, owo itanran ti i ṣe ẹgbẹrun lọna ogun Riyal, ( 20,000 riyal) owo ilu naa ni ẹni to ba lufin yii yoo san.

Ǹjẹ́ òfin fàyè gba Gómìnà láti fẹgbẹ́ òṣèlú rẹ̀ sílẹ̀ darapọ̀ mọ́ òmíràn? Ohun tí a mọ̀ rèé

Ǹjẹ́ òfin fàyè gba Gómìnà láti fẹgbẹ́ òṣèlú rẹ̀ sílẹ̀ darapọ̀ mọ́ òmíràn? Ohun tí a mọ̀ rèé

Ọjọ́ Àbámẹ́ta, 3 Oṣù Ẹ̀bibi 2025 ní 16:33:04

Amofin Yomi Aliu (SAN) sọ fun BBC Yoruba wi pe ofin to mu egungun naa lo mu ẹlẹha, eyi to tumọ si pe bawọn aṣofin ba le kuro ninu ẹgbẹ oṣelu to gbe wọn wọle ibo darapọ mọ ẹgbẹ mii to wu wọn, ko si nnkan to da awọn gomina naa duro lati ṣe bẹẹ.