world-service-rss

BBC News Yorùbá

Ààrẹ Tinubu ṣe àfikún iye owó ètò ìṣúná fún ọdún 2025

Ààrẹ Tinubu ṣe àfikún iye owó ètò ìṣúná fún ọdún 2025

Ọjọ́rú, 5 Oṣù Èrèlè 2025 ní 17:42:18

Eyi lo wa ninu lẹta kan ti aarẹ kọ si ile igbimọ aṣofin, Aarẹ Sẹnetọ Godswill Akpabio si ka fun gbogbo ọmọ ile igbimọ aṣofin lọjọbọ, ọjọ karun un oṣu keji ọdun 2025.

Ohun ta a mọ̀ nípa ọkùnrin tó ṣíná bolè fún èèyàn 11 tó sì tún pa ara rẹ̀ níta ilé ẹ̀kọ́

Ohun ta a mọ̀ nípa ọkùnrin tó ṣíná bolè fún èèyàn 11 tó sì tún pa ara rẹ̀ níta ilé ẹ̀kọ́

Ọjọ́rú, 5 Oṣù Èrèlè 2025 ní 18:37:55

Fọnran to jade lori ayelujara ṣafihan bi awọn akẹkọọ se n sa si abẹ tabili wọn lẹyin ti wọn gboro ibọn.

Ìjàmbá ina ṣekúpa akẹ́kọ̀ọ́ 17 ni Zamfara

Ìjàmbá ina ṣekúpa akẹ́kọ̀ọ́ 17 ni Zamfara

Ọjọ́rú, 5 Oṣù Èrèlè 2025 ní 14:26:35

Oṣojumikoro, Yahaya Mahi to ba akọroyin BBC sọrọ ni ina naa bẹrẹ ni ile kan to wa ni iwaju yara awọn akẹkọọ ko to di pe o tan mọ ile awọn akẹkọọ.

Òjò àrọ̀ọ̀rọ̀dá yóò wáyé ní Nàìjíríà láàrín óṣù karùn ún àti ìkẹfà - NiMET

Òjò àrọ̀ọ̀rọ̀dá yóò wáyé ní Nàìjíríà láàrín óṣù karùn ún àti ìkẹfà - NiMET

Ọjọ́rú, 5 Oṣù Èrèlè 2025 ní 13:21:48

Ajọ NiMET tun sọrọ pe ọwọ ojo yoo tunbọ pọ sii laarin oṣu karun un si ikẹfa ọdun 2025 lorilẹede Naijiria. O ni eyi yoo gbilẹ lawọn ilu to wa lẹsẹ odo lorilẹede Naijiria.

Ọba tó fìyà jẹ olóyè níta gbangba sun ọgbà ẹ̀wọ̀n mọ́jú lẹ́yìn tó kùnà láti mú ìlànà béèlì rẹ̀ ṣẹ

Ọba tó fìyà jẹ olóyè níta gbangba sun ọgbà ẹ̀wọ̀n mọ́jú lẹ́yìn tó kùnà láti mú ìlànà béèlì rẹ̀ ṣẹ

Ọjọ́rú, 5 Oṣù Èrèlè 2025 ní 11:40:12

Igbakeji agbẹnusọ ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Ogun lo fidi ọrọ yii mulẹ ninu ifọrọwerọ kan to ṣe pẹlu awọn akọroyin laarọ Ọjọru ọjo karun un oṣu Keji ọdun yii.

Kò ṣeé má gbọ̀ọ́

Kò ṣeé má gbọ̀ọ́

Ọjọ́rú, 5 Oṣù Èrèlè 2025 ní 12:41:10

Wọ́nyi ni àwọn kò ṣeé má gbọ̀ọ́ ìròyìn káàkiri àgbáyé

Ọkọ àti ìyàwó rí òkú ọmọ wọn mẹ́ta tí wọ́n ń wá nínú ẹ̀rọ́ yìnyín ‘freezer’, ọlọ́pàá bẹ̀rẹ̀ ìwádìí

Ọkọ àti ìyàwó rí òkú ọmọ wọn mẹ́ta tí wọ́n ń wá nínú ẹ̀rọ́ yìnyín 'freezer', ọlọ́pàá bẹ̀rẹ̀ ìwádìí

Ọjọ́rú, 5 Oṣù Èrèlè 2025 ní 10:37:07

Ọgbẹni Udochukwu Samuel Ejezie to jẹ baba awọn ọmọ naa sọ fun BBC pe iṣẹlẹ ọhun waye lẹyin ile iwosan fasiti ẹkọṣẹ iṣẹgun Nnamdi Azikwe niluu Nnenwi.

Gómìnà Adeleke sọ̀rọ̀ lórí rògbòdìyàn tó bẹ́ sílẹ̀ nílùú Esa Oke, Ọba Owamiran ń bèèrè fún ìdájọ́ òdodo

Gómìnà Adeleke sọ̀rọ̀ lórí rògbòdìyàn tó bẹ́ sílẹ̀ nílùú Esa Oke, Ọba Owamiran ń bèèrè fún ìdájọ́ òdodo

Ọjọ́rú, 5 Oṣù Èrèlè 2025 ní 08:53:59

Nigba ti gomina Ademola Adeleke n ba awọn ọmọ iluu Esa-oke sọrọ, o fi da wọn loju wi pe, ẹnikẹni to ba wa nidi Isẹlẹ naa yoo fimu ko ata ofin.

Wo ohun tó fa awuyewuye lórí ìfẹ̀yìntì àti ọjọ́ orí ọ̀gá ọlọ́pàá Nàìjíríà, Kayode Egbetokun

Wo ohun tó fa awuyewuye lórí ìfẹ̀yìntì àti ọjọ́ orí ọ̀gá ọlọ́pàá Nàìjíríà, Kayode Egbetokun

Ọjọ́rú, 5 Oṣù Èrèlè 2025 ní 06:50:47

Oṣu Kẹsan-an ọdun 2024 ni Kayode Egbetokun pe ọgọta ọdun looke eepẹ.

Lórí ọ̀rọ̀ ikú Bola Ige, Bisi Akande, Rashidi Ladoja sọ òkò ọ̀rọ̀ sí ara wọn

Lórí ọ̀rọ̀ ikú Bola Ige, Bisi Akande, Rashidi Ladoja sọ òkò ọ̀rọ̀ sí ara wọn

Ọjọ́ Ìsẹ́gun, 4 Oṣù Èrèlè 2025 ní 16:28:05

Ní òpin ọ̀sẹ̀ ni ìfọ̀rọ̀wérọ̀ kan tí Bisi Akande ṣe pẹ̀lú akọ̀ròyìn Edmund Obilo gba orí ayélujára níbi tí Akande ti sọ pé Ladoja nímọ̀ nípa àwọn nǹkankan lórí ikú Bola Ige.

Ọba tó fìyà jẹ olóyè níta gbangba sun ọgbà ẹ̀wọ̀n mọ́jú lẹ́yìn tó kùnà láti mú ìlànà béèlì rẹ̀ ṣẹ

Ọba tó fìyà jẹ olóyè níta gbangba sun ọgbà ẹ̀wọ̀n mọ́jú lẹ́yìn tó kùnà láti mú ìlànà béèlì rẹ̀ ṣẹ

Ọjọ́rú, 5 Oṣù Èrèlè 2025 ní 11:40:12

Igbakeji agbẹnusọ ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Ogun lo fidi ọrọ yii mulẹ ninu ifọrọwerọ kan to ṣe pẹlu awọn akọroyin laarọ Ọjọru ọjo karun un oṣu Keji ọdun yii.

Ilé ẹjọ́ dájọ́ ikú fún awakọ̀ tó pa tọkọtaya tó jẹ́ ọ̀gá rẹ̀ lọ́jọ́ ọdún tuntun

Ilé ẹjọ́ dájọ́ ikú fún awakọ̀ tó pa tọkọtaya tó jẹ́ ọ̀gá rẹ̀ lọ́jọ́ ọdún tuntun

Ọjọ́ Ìsẹ́gun, 4 Oṣù Èrèlè 2025 ní 12:50:20

Ní ọjọ́ Kìíní, oṣù Kìíní, ọdún 2023 ni àwọn ọ̀daràn náà lọ ká àwọn tọkọtaya náà mọ́lé lẹ́yìn tí wọ́n dárí ìsìn láti bọ́ sínú ọdún tuntun.

Ikọ̀ ọmọogun ọlọ̀tẹ̀ kéde ìdádúró ogun ní DR Congo kí àwọn ohun ìrànwọ́ lè wọlé fáráàlú

Ikọ̀ ọmọogun ọlọ̀tẹ̀ kéde ìdádúró ogun ní DR Congo kí àwọn ohun ìrànwọ́ lè wọlé fáráàlú

Ọjọ́ Ìsẹ́gun, 4 Oṣù Èrèlè 2025 ní 13:34:54

Aarẹ orilẹede Rwanda ati Congo yoo peju sibi ipade alaafia ajọ awọn orilẹede to wa lẹkun naa ti yoo waye ni orilẹede Tanzania lọjọ Ẹti.

Gómìnà Ìjọba Ogun ní kí ọba tó dá olóyé dọ̀bálẹ̀ níta gbangba lọ rọ́ọ́kún nílé, ọlọ́pàá fọ̀rọ̀ wá Kábíyèsí lẹ́nu wò

Gómìnà Ìjọba Ogun ní kí ọba tó dá olóyé dọ̀bálẹ̀ níta gbangba lọ rọ́ọ́kún nílé, ọlọ́pàá fọ̀rọ̀ wá Kábíyèsí lẹ́nu wò

Ọjọ́ Ìsẹ́gun, 4 Oṣù Èrèlè 2025 ní 09:55:41

Ijọba ipinlẹ Ogun sọ pe igbesẹ idaduro Olorile-Ifo, Oba Abdulsemiu Ogunjobi, ko ṣẹyin awọn ọrọ kobakungbe ati aṣemaṣe ti kabiyesi naa ṣe ninu fidio to lu ori ayelujara pa.

‘Àìsàn jẹjẹrẹ gba ohùn àti ìgbéyàwó lọ́wọ́ mi’

'Àìsàn jẹjẹrẹ gba ohùn àti ìgbéyàwó lọ́wọ́ mi'

Ọjọ́ Ìsẹ́gun, 4 Oṣù Èrèlè 2025 ní 09:39:13

Àjọ tó ń rí sí ètò ìlera àgbáyé, World Health Organization, WHO ní èèyàn mílíọ̀nù kan ó lé ọgọ́rùn-ún kan ló máa ń ní àìsàn jẹjẹrẹ nílẹ̀ Áfíríkà ní ọdọọdún àti pé èèyàn 700,000 ló máa ń ba lọ.

Ìdí tí ẹgbẹ́ òṣìṣẹ́ NLC fi fagilé ìwọde tí wọ́n fẹ́ bẹ̀rẹ̀ lónìí lórí àfikún tàríìfù orí ìpè àti dátà

Ìdí tí ẹgbẹ́ òṣìṣẹ́ NLC fi fagilé ìwọde tí wọ́n fẹ́ bẹ̀rẹ̀ lónìí lórí àfikún tàríìfù orí ìpè àti dátà

Ọjọ́ Ìsẹ́gun, 4 Oṣù Èrèlè 2025 ní 06:35:37

Ṣaaju ninu atẹjade kan ti aarẹ ẹgbẹ naa, Joe Ajaero, buwọlu ni NLC ti kede igbesẹ yii nibi ipade igbimọ alaṣẹ ẹgbẹ naa to waye l’ọjọ kọkandinlọgbọn oṣu Kinni yii niluu Abuja.

Rògbòdìyàn bẹ́ sílẹ̀ nílùú Esa Oke, ọlọ́pàá méje fara gba ọta ìbọn

Rògbòdìyàn bẹ́ sílẹ̀ nílùú Esa Oke, ọlọ́pàá méje fara gba ọta ìbọn

Ọjọ́ Ajé, 3 Oṣù Èrèlè 2025 ní 17:53:07

Ohun ti a ri gbọ ni pe awọn eeyan ilu ti kesi ijọba pe ko gbe baale ilu sipo Oba gẹgẹ bii Olojudo ti ilu Ido Ayegunle, ko si ma yan olori tuntun fun wọn.

Ohun tó yẹ kó o mọ̀ nípa ‘3rd Party Insurance’ àti bí o ṣe lè gbà á

Ohun tó yẹ kó o mọ̀ nípa '3rd Party Insurance' àti bí o ṣe lè gbà á

Ọjọ́ Ajé, 3 Oṣù Èrèlè 2025 ní 15:38:32

O kere tan, awọn araalu gbọdọ ṣe oriṣi inṣọransi ti oloyinbo n pe ni Third-party, gẹgẹ bi aṣẹ ọga ọlọpaa Naijiria

BBC ṣàbẹ̀wò sí Goma, ibi táwọn ọmọ ogun ọlọ̀tẹ̀ M23 ti ń ṣèjọba

BBC ṣàbẹ̀wò sí Goma, ibi táwọn ọmọ ogun ọlọ̀tẹ̀ M23 ti ń ṣèjọba

Ọjọ́ Ajé, 3 Oṣù Èrèlè 2025 ní 13:51:03

Kò dín ní ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin (700) èèyàn tó pàdánù ẹ̀mí wọn nínú ìkọlù náà, táwọn bíi ẹgbẹ̀rún mẹ́ta (3,000) èèyàn mìíràn sì tún farapa gẹ́gẹ́ bí àjọ ìṣọ̀kan àgbáyé, UN àti ìjọba Congo ṣe sọ.

Ìjọba Nàìjíríà yí ohùn padà, wọ́n ní irọ́ ni pé àwọn fẹ́ fowó kún owó iná mọ̀nàmọ̀nà

Ìjọba Nàìjíríà yí ohùn padà, wọ́n ní irọ́ ni pé àwọn fẹ́ fowó kún owó iná mọ̀nàmọ̀nà

Ọjọ́ Ajé, 3 Oṣù Èrèlè 2025 ní 13:22:38

Lọdun 2024 ni ijọba ti kọkọ fi kun owo ina lorilẹede NAijiria

Wo ìtàn tó bí oríkì ‘ìjàkadì lorò Offa’, àti bí wọ́n ṣe ń jà á

Wo ìtàn tó bí oríkì 'ìjàkadì lorò Offa', àti bí wọ́n ṣe ń jà á

Ọjọ́ Ajé, 3 Oṣù Èrèlè 2025 ní 09:45:58

Bi o tilẹ jẹ pe itan ni ijakadi naa, o ti di ayẹyẹ ọdọọdun ni ilu Offa bayii.

Àwọn aláìmọ̀kan ló ń tako ìdásílẹ̀ ìgbìmọ̀ Sharia nílẹ̀ Yorùbá - Shittu

Àwọn aláìmọ̀kan ló ń tako ìdásílẹ̀ ìgbìmọ̀ Sharia nílẹ̀ Yorùbá - Shittu

Ọjọ́ Àìkú, 2 Oṣù Èrèlè 2025 ní 11:26:33

Ní nǹkan bíi ọ̀sẹ̀ mélòó kan sẹ́yìn ni ọ̀rọ̀ ìdásílẹ̀ ìgbìmọ̀ Sharia ti ń fa awuyewuye káàkiri ilẹ̀ Yorùbá.

Èèyàn 28 jóná kọjá àlà níbi ìṣẹ̀lẹ̀ ìjàmbá ọkọ̀ l’Ondo

Èèyàn 28 jóná kọjá àlà níbi ìṣẹ̀lẹ̀ ìjàmbá ọkọ̀ l'Ondo

Ọjọ́ Àìkú, 2 Oṣù Èrèlè 2025 ní 18:15:31

Iṣẹlẹ naa waye ni ijọba ibilẹ Odigbo ni irọlẹ ọjọ Satide ọjọ kinni oṣe keji ọdun 2025.

Kí ló ń fa ìfànfà láàárín Gómìnà Adeleke àti Ọba ìlú Iragbiji lórí oyè Aragbiji?

Kí ló ń fa ìfànfà láàárín Gómìnà Adeleke àti Ọba ìlú Iragbiji lórí oyè Aragbiji?

Ọjọ́ Àìkú, 2 Oṣù Èrèlè 2025 ní 10:40:16

Àṣẹ náà ní ìdílé Lagbua ló máa jẹ́ ìdílé karùn-ún, tí yóò sì máa jẹ ọba kẹ́yìn lásìkò tí ìyànsípò ọba yóò bá wáyé.

Wo ipa tí àdínkù owó epo bẹntiróòlù tí Dangote ṣẹ̀ṣẹ̀ kéde yóò ní lórí aráàlú

Wo ipa tí àdínkù owó epo bẹntiróòlù tí Dangote ṣẹ̀ṣẹ̀ kéde yóò ní lórí aráàlú

Ọjọ́ Àìkú, 2 Oṣù Èrèlè 2025 ní 09:50:57

Gẹgẹ ti atẹjade kan ti ileeṣẹ Dangote fi sita, lati ọjọ Abamẹta ọjọ kinni oṣu Keji ọdun yii ni adinku ti ba owo epo bẹntiroolu.

Àwọn ọmọ Naijiria tí kò níwèé ìgbélùú l’America ń sá kiri- Ìwádìí

Àwọn ọmọ Naijiria tí kò níwèé ìgbélùú l'America ń sá kiri- Ìwádìí

Ọjọ́ Àbámẹ́ta, 1 Oṣù Èrèlè 2025 ní 17:46:40

Ọpọ awọn eeyan yii lo ni igbagbọ pe o ṣeeṣe ki wọn ma fi wọn sọwọ pada si orilẹede Naijiria titi wọ asiko ti Aarẹ Trump yoo fi yi ipinnu rẹ pada.

‘Ìdí tí mo fi máa ń sunkún nínú fíìmù nígbà tí mo bẹ̀rẹ̀ eré nìyí’

'Ìdí tí mo fi máa ń sunkún nínú fíìmù nígbà tí mo bẹ̀rẹ̀ eré nìyí'

Ọjọ́ Àbámẹ́ta, 1 Oṣù Èrèlè 2025 ní 08:23:29

Lateef Adedimeji, nínú ìfọ̀rọ̀wérọ̀ kan tó ṣe pẹ̀lú iléeṣẹ́ ìròyìn The Punch ní òun mọ̀ọ́mọ̀ kó ipá ẹlẹ́kún nígbà tí òun bẹ̀rẹ̀ eré láti lè ní ohun ìdánimọ̀ kan pàtó tí àwọn èèyàn yóò mọ òun mọ́.

A ti ń kọ́ àwọn dókítà mí-ìn níṣẹ́ làti rọ́pò àwọn tó ń jápa- Mínísítà ètò ìlera

A ti ń kọ́ àwọn dókítà mí-ìn níṣẹ́ làti rọ́pò àwọn tó ń jápa- Mínísítà ètò ìlera

Ọjọ́ Àbámẹ́ta, 1 Oṣù Èrèlè 2025 ní 08:40:41

Ninu ifọrọwerọ kan ti Ọjọgbọn Pate to tun wa fun ọrọ igbayegbadun araalu, ṣe pẹlu BBC lo ti sọ pe bawọn kan tiẹ n japa, awọn iṣi mi-in tun wa ti yoo rọpo wọn.

Ọkọ̀ òfurufú tó gbé ọmọ tó ń ṣàárẹ̀, ìyá rẹ̀, àtàwọn míì já lulẹ̀ ní US

Ọkọ̀ òfurufú tó gbé ọmọ tó ń ṣàárẹ̀, ìyá rẹ̀, àtàwọn míì já lulẹ̀ ní US

Ọjọ́ Àbámẹ́ta, 1 Oṣù Èrèlè 2025 ní 12:08:25

Ọkọ̀ òfurufú náà ló ń gbé ọmọ tó ń ṣe àárẹ̀, ìyá rẹ̀ àtàwọn òṣìṣẹ́ ìrìnnà òfurufú náà ló wà nínú rẹ̀ lásìkò tí ìjákulẹ̀ náà wáyé.

MURIC ní Shariah ti bẹ̀rẹ̀ n’Ibadan, Eko àti Abeokuta, àjọ CAN, Afenifere àtàwọn oníṣẹ̀ṣe fèsì sọ́rọ̀ Sultan

MURIC ní Shariah ti bẹ̀rẹ̀ n'Ibadan, Eko àti Abeokuta, àjọ CAN, Afenifere àtàwọn oníṣẹ̀ṣe fèsì sọ́rọ̀ Sultan

Ọjọ́ Ẹtì, 31 Oṣù Ṣẹ́rẹ́ 2025 ní 13:50:48

Alaga ajọ CAN ni Gomina Seyi Makinde ti fi erongba rẹ han lori ọrọ Shari’ah pe iwe ofin orilẹede Naijiria nikan loun mọ nipinle Oyo.

Ilé ẹjọ́ gba onídùúró Sowore pẹ̀lú mílíọ́nù mẹ́wàá náírà

Ilé ẹjọ́ gba onídùúró Sowore pẹ̀lú mílíọ́nù mẹ́wàá náírà

Ọjọ́ Ẹtì, 31 Oṣù Ṣẹ́rẹ́ 2025 ní 15:37:43

Adajọ paṣẹ pe oniduuro naa gbọdọ fi iwe irinna rẹ silẹ fun kootu, o si gbọdọ bura fun kootu pẹlu.

Èyí ni àwọn ìwé tí o gbọ́dọ̀ ní bí o kò bá fẹ́ kí wọ́n dá ọ padà sílé láti America

Èyí ni àwọn ìwé tí o gbọ́dọ̀ ní bí o kò bá fẹ́ kí wọ́n dá ọ padà sílé láti America

Ọjọ́ Ẹtì, 31 Oṣù Ṣẹ́rẹ́ 2025 ní 12:32:46

Iroyin naa sọ pe awọn ọmọ Naijiria lo wa nipo keji ninu awọn to n japa ju.

Ìtàn Mánigbàgbé nípa Olorì Luwoo Gbagida obìnrin tó ṣáájú àsìkò rẹ̀ jẹ Ooni Ife tó sì tún jẹ́ alágbára nílẹ̀ Yorùbá

Ìtàn Mánigbàgbé nípa Olorì Luwoo Gbagida obìnrin tó ṣáájú àsìkò rẹ̀ jẹ Ooni Ife tó sì tún jẹ́ alágbára nílẹ̀ Yorùbá

Ọjọ́ Àìkú, 2 Oṣù Èrèlè 2025 ní 08:30:54

Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ìtàn to pọ̀ lóde kò fi bẹ́ẹ̀ dárúkọ rẹ̀, nítorí pé ìtàn àtẹnudẹ̀nu ló pọ̀jù nínú ìtàn orile-ede Naijiria, ọ̀pọ̀ sí ló máa ń sọ ìtàn bí ẹni pé ọkùnrin nìkan ló n jẹ Ooni Ife.

Ilé ẹjọ́ yí àṣẹ Gómìnà Adeleke padà lórí ìyànsípò Owa ti Igbajo

Ilé ẹjọ́ yí àṣẹ Gómìnà Adeleke padà lórí ìyànsípò Owa ti Igbajo

Ọjọ́ Àbámẹ́ta, 1 Oṣù Èrèlè 2025 ní 10:31:30

Ní ọjọ́rú, ọgbọ̀n ọjọ́, oṣù Kìíní, ọdún 2025 ni Adájọ́ AO Ayoola ti ilé ẹjọ́ gíga ìpínlẹ̀ Osun gbé ìdájọ́ kalẹ̀ pé bí ìjọba ṣe yọ Ọba Famodun kò tọ̀nà rárá.

Awakọ̀ tó ń wa ‘ìwàkuwà’ kọlu àwọn ológun tó ń yan fanda l’Eko, ológun kan kú, ọ̀pọ̀ farapa

Awakọ̀ tó ń wa 'ìwàkuwà' kọlu àwọn ológun tó ń yan fanda l'Eko, ológun kan kú, ọ̀pọ̀ farapa

Ọjọ́ Ẹtì, 31 Oṣù Ṣẹ́rẹ́ 2025 ní 15:23:24

Olabisi Ayeni, to jẹ igbakeji agbẹnusọ ileeṣẹ naa lo fi ikede ọhun sita.

“Nítorí mo tako ìjọba, wọ́n gbé mi lọ sílé ìwòsàn fún ìtọ́jú àrùn ọpọlọ”

"Nítorí mo tako ìjọba, wọ́n gbé mi lọ sílé ìwòsàn fún ìtọ́jú àrùn ọpọlọ"

Ọjọ́ Ẹtì, 31 Oṣù Ṣẹ́rẹ́ 2025 ní 14:25:31

Junjie jẹ ọkan ninu ọpọ eeyan ti BBC ba sọrọ lẹyin ti wọn dero ile iwosan aarun ọpọlọ lẹyin ti wọn se ifẹhonuhan tako ijọba.

Ètò ìsìnkú Moses Korede, tí ọ̀pọ̀ mọ sì Bàbá Gbenro, tí bẹrẹ nilu Ogbomoso

Ètò ìsìnkú Moses Korede, tí ọ̀pọ̀ mọ sì Bàbá Gbenro, tí bẹrẹ nilu Ogbomoso

Ọjọ́ Ẹtì, 31 Oṣù Ṣẹ́rẹ́ 2025 ní 09:18:12

Agba osere Kristiẹni ni Korede Are nigba aye rẹ, to si ti kopa ninu ọpọ sinima Kristiẹni, ki ọlọjọ to de.

Ijọba àpapọ̀ fún ẹbí Alàgbà Akinkunmi tó ṣe asia Naijiria ní mílíọ́nù lọ́nà ọgbọ̀n náírà

Ijọba àpapọ̀ fún ẹbí Alàgbà Akinkunmi tó ṣe asia Naijiria ní mílíọ́nù lọ́nà ọgbọ̀n náírà

Ọjọ́ Ẹtì, 31 Oṣù Ṣẹ́rẹ́ 2025 ní 10:51:16

Ninu ọrọ ọga agba NOA, o ni owo ti ijọba apapọ fun mọlẹbi Oloogbe naa ki i ṣe owo ọya fun awọn iṣẹ to ṣe nigba aye rẹ, bi ko ṣe lati ṣe iranlọwọ fun ẹbi rẹ nitori ipa rere to ko lorilẹede yii.

Aráàlú yìnbọn pa ọmọ ilẹ̀ Iraq tó dáná sun Quran, ọlọ́pàá bẹ̀rẹ̀ ìwádìí

Aráàlú yìnbọn pa ọmọ ilẹ̀ Iraq tó dáná sun Quran, ọlọ́pàá bẹ̀rẹ̀ ìwádìí

Ọjọ́ Ẹtì, 31 Oṣù Ṣẹ́rẹ́ 2025 ní 07:10:59

Ọdun 2023 ni oloogbe naa dana sun iwe mimọ awọn Musulumi niwaju mọṣalaṣi nla Stockholm Central Mosque.

Ìdílé kan rèé tó fi iṣẹ́ sàárè gbígbẹ́ ṣe iṣẹ́ ìrandíran láì gba kọ́bọ̀

Ìdílé kan rèé tó fi iṣẹ́ sàárè gbígbẹ́ ṣe iṣẹ́ ìrandíran láì gba kọ́bọ̀

Ọjọ́bọ, 30 Oṣù Ṣẹ́rẹ́ 2025 ní 10:10:48

BBC bá ìdílé kan pàdé tó ń gbẹ́ sàárè fún ọpọ̀ ọdún láì gba owó oṣù tàbí owó ọ̀yà.

Tinubu kò fẹ́ dupò ààrẹ, gbogbo ẹni tó ń rọ̀ ọ́ láti díje, ló ń bá jà, èmi ni mo paṣẹ pé kó díje - Bisi Akande

Tinubu kò fẹ́ dupò ààrẹ, gbogbo ẹni tó ń rọ̀ ọ́ láti díje, ló ń bá jà, èmi ni mo paṣẹ pé kó díje - Bisi Akande

Ọjọ́bọ, 30 Oṣù Ṣẹ́rẹ́ 2025 ní 11:50:36

Bisi Akande ní òun sọ fún Tinubu pé ìran Yorùbá ló fẹ́ ṣe ààrẹ fún, pé kìí ṣe nítorí ara rẹ̀ ni àwọn ṣe ní kó díje.

Wọn rí òkú èrò 19 nínú ìjàmbá bàálù méjì tó forí sọra l‘ófurufú, tó já bọ́ sínú odò

Wọn rí òkú èrò 19 nínú ìjàmbá bàálù méjì tó forí sọra l‘ófurufú, tó já bọ́ sínú odò

Ọjọ́bọ, 30 Oṣù Ṣẹ́rẹ́ 2025 ní 06:12:25

Isẹlẹ naa lo waye lasiko ti baalu akero naa fẹ ba lopopona baalu kẹtalelọgbọn, ti iwadi si ti n lọ nipa ohun to fa isẹlẹ naa.

Ìdí rèé tí Makinde fi ní káwọn òṣìṣẹ́ Oyo máa wọ Aṣọ Òkè ní gbogbo Ọjọ́bọ

Ìdí rèé tí Makinde fi ní káwọn òṣìṣẹ́ Oyo máa wọ Aṣọ Òkè ní gbogbo Ọjọ́bọ

Ọjọ́bọ, 30 Oṣù Ṣẹ́rẹ́ 2025 ní 10:44:06

Gẹgẹ bii atẹjade kan to wa lati ọfiisi adari oṣiṣẹ nipinlẹ Oyo ṣe sọ, wiwọ asọ oke lọ si ọfiisi ni gbogbo Ọjọgbọ jẹ ọna lati se igbelarugẹ aṣa ati iṣe awọn eeyan ipinlẹ Oyo.

Ilé ẹjọ́ Sharia gbọdọ̀ wọ ìpínlẹ̀ Oyo àti Ekiti, òfin Naijiria faramọ́ kóòtù Sharia – Sultan Sokoto

Ilé ẹjọ́ Sharia gbọdọ̀ wọ ìpínlẹ̀ Oyo àti Ekiti, òfin Naijiria faramọ́ kóòtù Sharia – Sultan Sokoto

Ọjọ́bọ, 30 Oṣù Ṣẹ́rẹ́ 2025 ní 16:49:11

Sultan Sokoto fi kun pe ofin orilẹede Naijiria ti wọn kọ lọdun 1999 faye gba ile ẹjọ Sharia gẹgẹ bo ṣe faye gba ile ẹjọ ijọba to n da si aawọ laarin araalu.