world-service-rss

BBC News Yorùbá

Agbébọn yìnbọn pa alága Miyetti Allah Kwara níwájú ilé rẹ̀, ọlọ́pàá bẹ̀rẹ̀ ìwádìí

Agbébọn yìnbọn pa alága Miyetti Allah Kwara níwájú ilé rẹ̀, ọlọ́pàá bẹ̀rẹ̀ ìwádìí

Ọjọ́ Àìkú, 9 Oṣù Ẹrẹ̀nà 2025 ní 18:01:22

Àtẹ̀jáde tí agbẹnusọ ọlọ́pàá Kwara, Adetoun Ejire-Adeyemi fi léde lọ́jọ́ Àìkú fìdí ìṣẹ̀lẹ̀ náà múlẹ̀, tó sì sọ pé àwọn ọlọ́pàá bá ilé ọta ìbọn márùn-ún níwájú ilé náà.

Ohun mẹ́sàn-án nípa Lesotho, orílẹ̀èdè tí ‘ẹnìkan kò gbúròó rẹ̀ rí’

Ohun mẹ́sàn-án nípa Lesotho, orílẹ̀èdè tí 'ẹnìkan kò gbúròó rẹ̀ rí'

Ọjọ́ Àìkú, 9 Oṣù Ẹrẹ̀nà 2025 ní 14:34:10

Orilẹede kekere to wa ni Guusu ilẹ Africa ni Lesotho. O kun fun awọn oke, orilẹede South Africa lo si yi i ka porogodo.

“Ẹbí fi mí yáwó nítorí àìsàn, ni mo ṣe di ẹrú lóko igbó’’

"Ẹbí fi mí yáwó nítorí àìsàn, ni mo ṣe di ẹrú lóko igbó''

Ọjọ́ Àìkú, 9 Oṣù Ẹrẹ̀nà 2025 ní 11:46:08

Gẹgẹ bi alaye , nigba ti Baba Nam ni arun jẹjẹrẹ ẹdọforo, awọn ẹbi rẹ ya owo tiye rẹ jẹ £186,564 lọwọ olowo ele kan.

DR Congo kéde ẹ̀bùn $5m fún ẹnikẹ́ni tó bá báwọn mú olórí ọmọ ogun ọlọ̀tẹ̀

DR Congo kéde ẹ̀bùn $5m fún ẹnikẹ́ni tó bá báwọn mú olórí ọmọ ogun ọlọ̀tẹ̀

Ọjọ́ Àìkú, 9 Oṣù Ẹrẹ̀nà 2025 ní 15:17:18

Ní ọdún tó kọjá, ilé ẹjọ́ tó ń rí sí ọ̀rọ̀ àwọn ológún ṣe ìdájọ́ àwọn ọkpunrin mẹ́tẹ̀ẹ̀ta náà láì sí wón níbẹ̀, tí ilé ẹjọ́ náà sì dájọ́ ikú fún wọn fẹ́sùn ìdìtẹ̀ mọ́ ìjọba.

Afurasí yìnbọn pa alákòso WhatsApp nítorí tó yọ ọ́ lórí ìkànnì náà

Afurasí yìnbọn pa alákòso WhatsApp nítorí tó yọ ọ́ lórí ìkànnì náà

Ọjọ́ Àìkú, 9 Oṣù Ẹrẹ̀nà 2025 ní 07:03:46

Wọ́n ní Ashfaq àti Mushtaq ní ìfaǹfà lórí ìkànnì WhatsApp kan tí àwọn méjéèjì jọ wà èyí tó mú kí Mushtaq yọ Ashfaq lórí ìkànnì náà.

Kìí ṣe nítorí ẹ̀sùn ìbálòpọ̀ ni a ṣe ní kí Natasha lọ rọ́kún nílé, àwọn ẹ̀ṣẹ̀ márùn-ún tó ṣẹ̀ nìyí - Ilé aṣòfin

Kìí ṣe nítorí ẹ̀sùn ìbálòpọ̀ ni a ṣe ní kí Natasha lọ rọ́kún nílé, àwọn ẹ̀ṣẹ̀ márùn-ún tó ṣẹ̀ nìyí - Ilé aṣòfin

Ọjọ́ Àbámẹ́ta, 8 Oṣù Ẹrẹ̀nà 2025 ní 17:13:16

Bamidele nínú àtẹ̀jáde náà sọ pé àwọn ìwà àìtọ́ tí Natasha hù sílé aṣòfin ló fa ìjìyà tí ilé aṣòfin fún un.

Wo nǹkan mẹ́rin tó lè fa ikú òjijì fún èèyàn

Wo nǹkan mẹ́rin tó lè fa ikú òjijì fún èèyàn

Ọjọ́ Àbámẹ́ta, 8 Oṣù Ẹrẹ̀nà 2025 ní 15:18:44

Iku ko kan ọjọ ori, nitori ọmọ ọwọ n ku, bẹẹ ni ọdọ langba ti nnkan ko ṣe naa a maa ku lojiji.

Ọba ni mí, mi ò lè fẹ́yàwó kan- Portable

Ọba ni mí, mi ò lè fẹ́yàwó kan- Portable

Ọjọ́ Àbámẹ́ta, 8 Oṣù Ẹrẹ̀nà 2025 ní 13:05:26

Ninu ifọrọwerọ kan ti Were olorin ṣe pẹlu sọrọsọrọ ori afẹfẹ ti a mọ si Egungun laipẹ yii lo ti ni ṣina ọla ni ọpọ iyawo fifẹ jẹ.

Agbébọn yìnbọn mọ́ bààlúù UN, èèyàn mẹ́tàdínlọ́gbọ̀n kú

Agbébọn yìnbọn mọ́ bààlúù UN, èèyàn mẹ́tàdínlọ́gbọ̀n kú

Ọjọ́ Àbámẹ́ta, 8 Oṣù Ẹrẹ̀nà 2025 ní 11:22:36

Gẹgẹ bi UN ṣe wi, wọn ni ikọlu yii le pada di ogun.

Wo bí àwọn obiǹrin yìí ṣe dáhùn ìbéèrè láyàájọ́ àwọn obìnrin lágbàáyé fún 2025

Wo bí àwọn obiǹrin yìí ṣe dáhùn ìbéèrè láyàájọ́ àwọn obìnrin lágbàáyé fún 2025

Ọjọ́ Àbámẹ́ta, 8 Oṣù Ẹrẹ̀nà 2025 ní 08:24:38

Idahun awọn ibeere lori awọn akọni obinrin lorilẹede Naijiia, bi a ṣe n ṣe ajọyọ ayajọ awọn obinrin lagbaaye lonii, ọjọ kẹjọ, oṣu Kẹta ọdun 2025.

Aláàfin Oyo, Ọba AbdulAkeem Owoade bẹ̀rẹ̀ orò ìpèbí lẹ́yìn oṣù kan tó gba ọ̀pá àṣẹ

Aláàfin Oyo, Ọba AbdulAkeem Owoade bẹ̀rẹ̀ orò ìpèbí lẹ́yìn oṣù kan tó gba ọ̀pá àṣẹ

Ọjọ́ Àbámẹ́ta, 8 Oṣù Ẹrẹ̀nà 2025 ní 06:59:20

Olórí òṣìṣẹ́ sí Aláàfin tuntun náà, Rotimi Osuntola ló kéde èyí nínú àtẹ̀jáde kan tó fi léde lọ́jọ́ Ẹtì.

Darapọ̀ mọ́ wa lórí WhatsApp

Darapọ̀ mọ́ wa lórí WhatsApp

Ọjọ́ Ajé, 15 Oṣù Ìgbé 2024 ní 11:20:59

Má jẹ́ kí etí rẹ ó di sí gbogbo ìròyìn ohun tó ń lọ ní Naijiria àti káàkiri àgbáyé. Mọ̀ nípa wọn lórí ìkànnì Whatsapp rẹ

‘Ìfẹ́ tí mo ní sí ọ̀bọ ló jẹ́ kí n bẹ̀rẹ̀ eré ìdárayá lílo ọwọ́ àti ẹsẹ̀ fi sáré’

'Ìfẹ́ tí mo ní sí ọ̀bọ ló jẹ́ kí n bẹ̀rẹ̀ eré ìdárayá lílo ọwọ́ àti ẹsẹ̀ fi sáré'

Ọjọ́ Ẹtì, 7 Oṣù Ẹrẹ̀nà 2025 ní 14:35:54

Ito tó máa ń sáré pẹ̀lú ọwọ́ àti ẹsẹ̀ kílómítà ọgọ́rùn-ún láàárín ìṣẹ̀jú àáyá 15.71.

Wo àwọn ọba alayé tí wọ́n gba adé lórí wọn ní Nàíjíríà

Wo àwọn ọba alayé tí wọ́n gba adé lórí wọn ní Nàíjíríà

Ọjọ́ Àbámẹ́ta, 25 Oṣù Ẹ̀bibi 2024 ní 09:53:44

BBC Yoruba ti wa mu diẹ lara awọn ọba alaye ti ijọba tabi igbimọ to n ri sọrọ ọba lawọn ilu kọọkan ni Naijiria ti rọ nipo.

Àgbà òṣèlú, Dókítà Doyin Okupe jáde láyé

Àgbà òṣèlú, Dókítà Doyin Okupe jáde láyé

Ọjọ́ Ẹtì, 7 Oṣù Ẹrẹ̀nà 2025 ní 09:29:56

Ọjọ Ẹti oni tii se ọjọ Keje osu Kẹta ọdun 2025 ni Okupe jade laye lẹni ọdun mọkanlelaadọta.

Ó tẹ́ wa lọ̀rùn ká kú sódò, ju ká di ọmọ ogun ọlọ̀tẹ̀ lọ - Àwọn ọkùnrin Congo

Ó tẹ́ wa lọ̀rùn ká kú sódò, ju ká di ọmọ ogun ọlọ̀tẹ̀ lọ - Àwọn ọkùnrin Congo

Ọjọ́ Ẹtì, 7 Oṣù Ẹrẹ̀nà 2025 ní 11:03:39

‘Ó kéré tán, ogún èèyàn ló bá omi lọ lọ́sẹ̀ tó kọjá’ Gẹgẹ bi alaye awọn eeyan to n gbiyanju lati sa lọ naa, o kere tan, ogun eeyan ni omi gbe lọ lọsẹ to kọja lasiko ti wọn n wẹ lati sa wọ Burundi.

Wo orúkọ̀ èèyàn 17, tó fi mọ́ Simon Ekpa, tíjọba kéde pé wọn ń gbé owó kalẹ̀ fún ìgbésùnmọ̀mí

Wo orúkọ̀ èèyàn 17, tó fi mọ́ Simon Ekpa, tíjọba kéde pé wọn ń gbé owó kalẹ̀ fún ìgbésùnmọ̀mí

Ọjọ́ Ẹtì, 7 Oṣù Ẹrẹ̀nà 2025 ní 10:04:48

Ọjọbọ ni igbimọ to n ri si ifiya jẹ arufin kede eeyan mẹtadinlogun to n se onigbọwọ igbesunmọmi eyi to tako ofin to n gbogun ti igbesunmọmi ti ọdun 2022.

Àkọsílẹ̀ iye èèyàn tó bá ìkọlù agbébọn lọ ni 2024 rèé àti ipò tí Nàíjíríà wà nínú ìgbésùnmọ̀mí

Àkọsílẹ̀ iye èèyàn tó bá ìkọlù agbébọn lọ ni 2024 rèé àti ipò tí Nàíjíríà wà nínú ìgbésùnmọ̀mí

Ọjọ́ Ẹtì, 7 Oṣù Ẹrẹ̀nà 2025 ní 11:20:21

Ẹka Global Terrorism Index ṣalaye pe Naijiria ti sun kuro ni ipo kẹjọ to wa ni 2023 ati 2024, pẹlu alekun to ba odiwọn iwa ipá to waye, to ti goke di bayii.

Ìdí rèé tí ilé ẹjọ́ tó ga jùlọ fi lé Eleruwa, Ọba Adebayo Adegbola kúrò lórí ìtẹ́, kí Makinde tó yàn-án padà lẹ́yìn ọdún mẹ́fà

Ìdí rèé tí ilé ẹjọ́ tó ga jùlọ fi lé Eleruwa, Ọba Adebayo Adegbola kúrò lórí ìtẹ́, kí Makinde tó yàn-án padà lẹ́yìn ọdún mẹ́fà

Ọjọ́ Ẹtì, 7 Oṣù Ẹrẹ̀nà 2025 ní 08:42:35

BBC Yoruba tu itan wo yẹbẹyẹbẹ lati ran wa leti awọn koko ẹsun ti ile ẹjọ kotẹmilọrun we mọ Ọba Adegbola lọrun lọdun 2019, to fi ni ko yẹ lori itẹ Eleruwa.

Mi ò lórí ọkọ, mo lé lọ́gbọ̀n ọdún, kò sọ́kọ, kò sọ́mọ, mo fẹ́ ṣẹ́yún tí mo pàpà ní torí ẹni tó fún mi lóyún kò gbà á -Wasila Coded

Mi ò lórí ọkọ, mo lé lọ́gbọ̀n ọdún, kò sọ́kọ, kò sọ́mọ, mo fẹ́ ṣẹ́yún tí mo pàpà ní torí ẹni tó fún mi lóyún kò gbà á -Wasila Coded

Ọjọ́ Ẹtì, 7 Oṣù Ẹrẹ̀nà 2025 ní 06:37:03

Bimpe Akintunde ni oun fẹ ṣẹ oyun to ti ga sita, nitori ọkunrin toun loyun naa fun ko gba a rara, diẹ lo ku ki oun ba oyun naa lọ.

Wo bí ìgbẹ́jọ́ Alfa Abdurahman, afurasí tí wọ́n bá òkú Yetunde nílé rẹ̀ n’Ilorin, ṣe lọ lónìí

Wo bí ìgbẹ́jọ́ Alfa Abdurahman, afurasí tí wọ́n bá òkú Yetunde nílé rẹ̀ n'Ilorin, ṣe lọ lónìí

Ọjọ́bọ, 6 Oṣù Ẹrẹ̀nà 2025 ní 11:47:53

Igbẹjọ naa waye ni ile ẹjọ Majisireeti to wa ni idojukọ ile ẹjọ giga ipinlẹ Kwara niluu Ilorin .

Eleruwa tuntun gba ọ̀pá àṣẹ, ìwé ẹ̀rí

Eleruwa tuntun gba ọ̀pá àṣẹ, ìwé ẹ̀rí

Ọjọ́bọ, 6 Oṣù Ẹrẹ̀nà 2025 ní 16:45:45

Atẹjade ti Kọmiṣanna fun eto iroyin ati ilaniloye nipinlẹ Oyo, Dotun Oyelade, fi sita lo fidi eyi mulẹ.

Kí ló dé táwọn sọ́jà yabo àwọn òṣìṣẹ́ amúnáwá ní Ikeja, lù wọ́n lálùbami, tí wọn fi ń fo ògiri jáde lọ́ọ́fìsì?

Kí ló dé táwọn sọ́jà yabo àwọn òṣìṣẹ́ amúnáwá ní Ikeja, lù wọ́n lálùbami, tí wọn fi ń fo ògiri jáde lọ́ọ́fìsì?

Ọjọ́bọ, 6 Oṣù Ẹrẹ̀nà 2025 ní 13:00:23

Ni nnkan bii ago mẹjọ ku ogun iṣẹju ni a gbọ pe awọn sọja naa ya wọ olu ileeṣẹ apinaka IKEDC ti ko jina si ileeṣẹ ijọba ipinlẹ Eko ni Ikeja.

Natasha lulẹ̀ níwájú ìgbìmọ́ aṣòfin, wọ́n da ẹ̀sùn ìyọlẹ́nu fún ìbálòpọ̀ tó fi kan Akpabio nù

Natasha lulẹ̀ níwájú ìgbìmọ́ aṣòfin, wọ́n da ẹ̀sùn ìyọlẹ́nu fún ìbálòpọ̀ tó fi kan Akpabio nù

Ọjọ́rú, 5 Oṣù Ẹrẹ̀nà 2025 ní 13:21:45

Ìgbìmọ̀ tó ń rí sí ìwà ọmọlúàbí ní ilé aṣòfin àgbà da ẹjọ́ ti Natasha pè tako Akpabio nù lọ́jọ́rú, wọ́n ní ẹ̀sùn rẹ̀ kò lẹ́sẹ̀ nílẹ̀.

Ẹ̀rọ ló gé mi lọ́wọ́ lẹ́nu iṣẹ́ tí mo fi di ọlọ́wọ́ kan tó ń fi Gángan yin Ọlọ́run - Ayomide Moses

Ẹ̀rọ ló gé mi lọ́wọ́ lẹ́nu iṣẹ́ tí mo fi di ọlọ́wọ́ kan tó ń fi Gángan yin Ọlọ́run - Ayomide Moses

Ọjọ́bọ, 6 Oṣù Ẹrẹ̀nà 2025 ní 11:00:36

Ayomide Moses ni awọn ẹya ara rẹ pe perepere nibẹrẹ aye rẹ amọ lẹyin to pari iwe mẹwa ni isẹlẹ nla sẹlẹ, eyi to mu ọwọ rẹ kan lọ.

Àìsàn ẹ̀jẹ̀ rúru ló kọ́ ṣe ‘I Sho Pepper’’, ó ń pọ̀ ẹ̀jẹ̀ lórí ahọ́n, dákú fọ́jọ́ mẹ́sàn -án, kí ọlọ́jọ́ tó dé - Yetunde Ogunsola

Àìsàn ẹ̀jẹ̀ rúru ló kọ́ ṣe 'I Sho Pepper'', ó ń pọ̀ ẹ̀jẹ̀ lórí ahọ́n, dákú fọ́jọ́ mẹ́sàn -án, kí ọlọ́jọ́ tó dé - Yetunde Ogunsola

Ọjọ́bọ, 6 Oṣù Ẹrẹ̀nà 2025 ní 08:58:55

Ọdun 1972 ni Yetunde Ogunsola to jẹ ọmọbibi ilu Ilesha bẹrẹ ere tita lẹyin to darapọ mọ ẹgbẹ oṣere oloogbe ‘‘I Sho Pepper.’’

Wo àwọn àìsàn tó le ṣúyọ ní àgọ́ ara lásìkò ààwẹ̀

Wo àwọn àìsàn tó le ṣúyọ ní àgọ́ ara lásìkò ààwẹ̀

Ọjọ́ Ìsẹ́gun, 11 Oṣù Ìgbé 2023 ní 06:13:59

Lásìkò àwẹ̀, àwọn ènìyàn máa ń séra fún oúnjẹ jíjẹ, omi mímu àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ àmọ́ ẹ wo àwọn àrùn tó le ti ìdí ààwẹ̀ súyọ.

Ọ̀gá tẹ́lẹ̀ fún iléeṣẹ́ arìnrìnàjò tí ayé ń kígbe pé Boko Haram pa, ilé ìtura ló kú sí l’Abuja - Ọlọ́pàá

Ọ̀gá tẹ́lẹ̀ fún iléeṣẹ́ arìnrìnàjò tí ayé ń kígbe pé Boko Haram pa, ilé ìtura ló kú sí l'Abuja - Ọlọ́pàá

Ọjọ́bọ, 6 Oṣù Ẹrẹ̀nà 2025 ní 05:48:09

Atẹjade ti Alukoro ọlọpaa fun ilu Abuja, Josephine Adeh, buwọ lu, tẹsiwaju pe ko pẹ ti Parradang wọ yara rẹ ni alejo obinrin kan wa a ki i.

Ilé alájà mẹ́ta wó l’Ekoo, èèyàn méjì kú, mẹ́rìnlá farapa

Ilé alájà mẹ́ta wó l'Ekoo, èèyàn méjì kú, mẹ́rìnlá farapa

Ọjọ́bọ, 6 Oṣù Ẹrẹ̀nà 2025 ní 11:16:54

Ajọ to n ri si iṣẹlẹ pajawiri nipinlẹ Eko, LASEMA, sọ pe eeyan mẹfa ni awọn doola ẹmi wọn labẹ ile ti wọn n kọ lọwọ ọhun.

BBC fojú ṣe mẹ́rin bí wọn ti ń ṣàtúnṣe wáyà ojú òpó ìtàkùn àgbáyé tó bá bàjẹ́ lábẹ́ òkun

BBC fojú ṣe mẹ́rin bí wọn ti ń ṣàtúnṣe wáyà ojú òpó ìtàkùn àgbáyé tó bá bàjẹ́ lábẹ́ òkun

Ọjọ́rú, 5 Oṣù Ẹrẹ̀nà 2025 ní 11:26:46

BBC dara pọ mọ awọn osisẹ ileesẹ to n satunse kebu itakun agbaye to wa labẹ okun Ghana lati mọ bi wọn ti n se atunse awọn kebu inu okun naa.

‘Àwọn agbéṣùmọ̀mí lẹ́kùn Sahel Africa ló ń ṣekúpa èèyàn jù lágbàáyé’

'Àwọn agbéṣùmọ̀mí lẹ́kùn Sahel Africa ló ń ṣekúpa èèyàn jù lágbàáyé'

Ọjọ́rú, 5 Oṣù Ẹrẹ̀nà 2025 ní 16:46:06

Ẹkùn Sahel ní Afirika ní ìdá mọ́kànléláàádọ́ta (51%) nínú ìdá ọgọ́rùn-ún ikú látara ìgbéṣùmọ̀mí ti wáyé lọ́dún 2024.

Ó ṣeéṣe kí ìdajì àwọn èèyàn tó wà láyé sanra àsanjù tó bá fi máa di ọdún 2050

Ó ṣeéṣe kí ìdajì àwọn èèyàn tó wà láyé sanra àsanjù tó bá fi máa di ọdún 2050

Ọjọ́rú, 5 Oṣù Ẹrẹ̀nà 2025 ní 06:30:37

Èyí ló ń jẹyọ nínú àbọ̀ kan tí àjọ The Lancet ṣẹ̀ṣẹ̀ gbé jáde lórí ìwádìí tí wọ́n ṣe ní àwọn orílẹ̀ èdè tó lé ní igba.

UN figbe ta pé àwọn agbébọn ń fipá bá àwọn ọmọ ọdún kan lo pọ lásìkò ogun abẹ́lé ní Sudan

UN figbe ta pé àwọn agbébọn ń fipá bá àwọn ọmọ ọdún kan lo pọ lásìkò ogun abẹ́lé ní Sudan

Ọjọ́rú, 5 Oṣù Ẹrẹ̀nà 2025 ní 06:09:53

Ajọ Iṣọkan Agbaye, UN, lati ọdọ ẹka rẹ to n ri si ọrọ ọmọde; UNICEF, ni àwọn agbébọn ń fipá bá àwọn ọmọ ọdún kan lo pọ ni Sudan.

Iléepo Dangote àti NNPC bẹ̀rẹ̀ orogún òwò lórí àdínkú owó líta epo, wo àwọn tí orí ń ta

Iléepo Dangote àti NNPC bẹ̀rẹ̀ orogún òwò lórí àdínkú owó líta epo, wo àwọn tí orí ń ta

Ọjọ́ Ìsẹ́gun, 4 Oṣù Ẹrẹ̀nà 2025 ní 11:22:17

Ọpọ awọn alagbata epo lo sọ pe ileeṣẹ NNPCL ko tii sọ fawọn pe adinku ti ba iye tawọn yoo maa ta epo fawọn bayii.

Ìjàm̀bá okọ̀ gbẹ̀mí èèyàn mẹ́rìndínlógún ní Ogun

Ìjàm̀bá okọ̀ gbẹ̀mí èèyàn mẹ́rìndínlógún ní Ogun

Ọjọ́ Ìsẹ́gun, 4 Oṣù Ẹrẹ̀nà 2025 ní 17:08:41

Nǹkan bíi aago kan ọ̀sán ni ìjàm̀bá náà wáyé nígbà tí ọkọ̀ Mazda kan tó ní nọ́mbà KJA949YJ ṣàdédé gbiná.

Èmi àti ẹ̀gbọ́n mi, Ayodele Fayose ń yan odì ọ̀lọ́jọ́ pípẹ́, bí a kò bá sọ̀rọ̀ láyé, á pàdé lọ́run - Isaac Fayose

Èmi àti ẹ̀gbọ́n mi, Ayodele Fayose ń yan odì ọ̀lọ́jọ́ pípẹ́, bí a kò bá sọ̀rọ̀ láyé, á pàdé lọ́run - Isaac Fayose

Ọjọ́ Ìsẹ́gun, 4 Oṣù Ẹrẹ̀nà 2025 ní 09:39:35

BBC Yorùbá bá Isaac, tíí ṣe àbúrò gómìnà tẹ́lẹ̀ ní ìpínlẹ̀ Ekiti, Ayodele Fayose sọ̀rọ̀, ó ṣàlàyé àjọṣepọ̀ pẹ̀lú ẹ̀gbọ́n rẹ̀, ìdí tó ṣe ní aya àti ọmọ púpọ̀ pẹ̀lú ètò ìṣèlú.