world-service-rss

BBC News Yorùbá

A ò gba èsì ìbò tó gbé Oyebanji wọlé fún sáà kejì, ètò ìdìbò náà kún fún èrú - AAC

A ò gba èsì ìbò tó gbé Oyebanji wọlé fún sáà kejì, ètò ìdìbò náà kún fún èrú - AAC

Ọjọ́ Àìkú, 21 Oṣù Òkúdu 2026 ní 09:26:48

Atẹjade ti alaga ẹgbẹ oṣelu AAC tẹka ipinle Ekiti, Makinde Folorunso fi lede lọjọ Abamẹta, Ogunjọ, oṣu Kẹfa lẹyin ti eto idibo naa pari fẹsun kan pe awọn iwa ko tọ to waye nibi eto idbo naa ko kere.

Ṣé òótọ́ ni pé ajínigbé tu aláboyún àtàwọn ọmọ rẹ̀ sílẹ̀ lẹ́yìn tí Sunday Igboho fún wọn ní gbèdéke wákàtí méjì?

Ṣé òótọ́ ni pé ajínigbé tu aláboyún àtàwọn ọmọ rẹ̀ sílẹ̀ lẹ́yìn tí Sunday Igboho fún wọn ní gbèdéke wákàtí méjì?

Ọjọ́ Àìkú, 21 Oṣù Òkúdu 2026 ní 12:48:15

Fidio kan to wa lori ayelujara ṣafihan bawọn eeyan ṣe n fi ijo pade alaboyun kan, aburo rẹ atawọn ọmọ rẹ ti wọn gba itusilẹ kuro ni ahamọ awọn ajinigbe to n da agbegbe naa laamu.

Father’s Day: Kí ni pàtàkì àyájọ́ ọjọ́ bàbá àti ìtàn tó rọ̀ mọ?

Father's Day: Kí ni pàtàkì àyájọ́ ọjọ́ bàbá àti ìtàn tó rọ̀ mọ?

Ọjọ́ Àìkú, 21 Oṣù Òkúdu 2026 ní 09:50:25

Ọjọ Aiku kẹta ninu oṣu Kẹfa ni wọn maa n ṣa ayajọ naa ni ọpọ orilẹede.

Wo kókó ohun tó yẹ kí o mọ̀ nípa Abiodun Oyebanji, olùdíje gómìnà fẹ́gbẹ́ APC tó wọlé sáà kejì l’Ekiti

Wo kókó ohun tó yẹ kí o mọ̀ nípa Abiodun Oyebanji, olùdíje gómìnà fẹ́gbẹ́ APC tó wọlé sáà kejì l'Ekiti

Ọjọ́ Àìkú, 21 Oṣù Òkúdu 2026 ní 05:53:24

Apapọ ibo to ni jẹ 319, 224, òun sì lo ní ibo to pọ julọ ni gbogbo ìjọba ìbílẹ̀ merindinlogun to wa ni ìpínlẹ̀ Ekiti.

Biodun Oyebanji jawe olubori nínú ìdìbò gómìnà ìpínlẹ̀ Ekiti

Biodun Oyebanji jawe olubori nínú ìdìbò gómìnà ìpínlẹ̀ Ekiti

Ọjọ́ Àìkú, 21 Oṣù Òkúdu 2026 ní 02:29:03

Ajo INEC ti kede pe Biodun Oyebanji lo jawe olubori ninu idibo gomina nipinlẹ Ekiti to waye lojo Satide.

“Ilé-iṣẹ́ rédíò Agidigbo FM ni ẹ lè wó, ẹ ò lè wó Oriyomi Hamzat”

"Ilé-iṣẹ́ rédíò Agidigbo FM ni ẹ lè wó, ẹ ò lè wó Oriyomi Hamzat"

Ọjọ́ Àìkú, 21 Oṣù Òkúdu 2026 ní 05:12:00

Oriyomi ni bi nnkan ṣe n lọ lagbo òṣèlú nipinlẹ Oyo lọ jẹ koun sọrọ sita, papaa julọ tori awon to n dunkooko moun ati ileeṣẹ redio oun.

Ṣé lóòótọ́ nìjọba ìpínlẹ̀ Ogun ti fòfin de ayẹyẹ ìkẹ́kọ̀ọ́jáde ilé ẹ̀kọ́ girama àti alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀? Ohun tí a mọ̀ rèé

Ṣé lóòótọ́ nìjọba ìpínlẹ̀ Ogun ti fòfin de ayẹyẹ ìkẹ́kọ̀ọ́jáde ilé ẹ̀kọ́ girama àti alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀? Ohun tí a mọ̀ rèé

Ọjọ́ Àìkú, 21 Oṣù Òkúdu 2026 ní 05:24:03

Ijọba ṣalaye ninu atẹjade ti ẹka to n ri si eto ẹkọ, sayẹnsi ati imọ ijinlẹ fi sita pe kii ṣe awọn akẹkọọjade ile ẹkọ girama, ati tawọn alakọọbẹrẹ ni ijọba ti fofin de.

Elebuibon fún Oluwo lésì, ní àwọn ọba ni kò ṣe ojúṣe wọn mọ́ tí ètò ààbò fi mẹ́hẹ

Elebuibon fún Oluwo lésì, ní àwọn ọba ni kò ṣe ojúṣe wọn mọ́ tí ètò ààbò fi mẹ́hẹ

Ọjọ́ Àbámẹ́ta, 20 Oṣù Òkúdu 2026 ní 12:29:19

Oluwo ni ti awọn babalawo ba kọ lati ṣe bẹẹ, oun ko gbọdọ pe babalawo kankan n halẹ mọ ẹnikankan mọ nilẹ Yoruba.

Àkójọpọ̀ ìròyìn bó ṣe ń lọ nínú ìdìbò gómìnà ìpínlẹ̀ Ekiti

Àkójọpọ̀ ìròyìn bó ṣe ń lọ nínú ìdìbò gómìnà ìpínlẹ̀ Ekiti

__

Ìròyìn àtìgbàdégbà nípa ìdìbò gómìnà ìpínlẹ̀ Ekiti

Àbọ̀ ìwádìí ọlọ́pàá rèé lórí afurasí agbénipa tó fẹ́ gbẹ̀mí Kábíyèsí Ataoja ìlú Osogbo láàfin

Àbọ̀ ìwádìí ọlọ́pàá rèé lórí afurasí agbénipa tó fẹ́ gbẹ̀mí Kábíyèsí Ataoja ìlú Osogbo láàfin

Ọjọ́ Àbámẹ́ta, 20 Oṣù Òkúdu 2026 ní 15:02:32

Ikede yii jade ti igbimọ oluwadii eyi ti igbakeji kọmiṣọna, DCP Suleiman Kafar Bayonle, to n ri si iwadii iwa ọdaran dari jabọ iwadii wọn.

Mọ̀ nípa nǹkan mẹ́fà tí kò tí ì lójútùú fáwọn olóṣèlú Nàìjíríà bí ìbò ọdún 2027 ṣe ń súnmọ́lé

Mọ̀ nípa nǹkan mẹ́fà tí kò tí ì lójútùú fáwọn olóṣèlú Nàìjíríà bí ìbò ọdún 2027 ṣe ń súnmọ́lé

Ọjọ́ Ẹtì, 19 Oṣù Òkúdu 2026 ní 17:47:59

Bi awon ẹgbẹ oṣelu to laami-laaka ṣe n koju wahala tiwọn ni awọn ẹgbẹ alatako naa n koju rogbodiyan abẹle to n da wọn laamu.

Darapọ̀ mọ́ wa lórí WhatsApp

Darapọ̀ mọ́ wa lórí WhatsApp

Ọjọ́ Ajé, 15 Oṣù Ìgbé 2024 ní 11:20:59

Má jẹ́ kí etí rẹ ó di sí gbogbo ìròyìn ohun tó ń lọ ní Naijiria àti káàkiri àgbáyé. Mọ̀ nípa wọn lórí ìkànnì Whatsapp rẹ

Ìjọba àpapọ̀ Nàìjíríà buwọ́lu N500bn owó ètò ààbò pàjáwìrì láti ṣẹ́gun ìgbésùnmọ̀mí

Ìjọba àpapọ̀ Nàìjíríà buwọ́lu N500bn owó ètò ààbò pàjáwìrì láti ṣẹ́gun ìgbésùnmọ̀mí

Ọjọ́ Ẹtì, 19 Oṣù Òkúdu 2026 ní 14:55:31

Ọjọbọ, ọjọ kejidinlogun oṣu Kẹfa ọdun 2026 yii ni igbesẹ naa waye.

Gbogbo kọ̀rọ̀kọ́ndú ìpinlẹ̀ Ekiti ni a ti fi ọlọ́pàá ṣọwọ́ sí fún ètò ìdìbò ọjọ́ Abamẹta - Ọlọ́pàá

Gbogbo kọ̀rọ̀kọ́ndú ìpinlẹ̀ Ekiti ni a ti fi ọlọ́pàá ṣọwọ́ sí fún ètò ìdìbò ọjọ́ Abamẹta - Ọlọ́pàá

Ọjọ́ Ẹtì, 19 Oṣù Òkúdu 2026 ní 09:38:12

CP Abayomi Shogunle salaye pe ileeṣẹ ọlọpaa ti fi awọn oṣiṣẹ agbofinro ranṣẹ s’awọn ibi to yẹ káàkiri ipinle Ekiti lati ṣe aridaju eto aabo to peye.

Àìsàn ‘sickle cell’ bá mi fínra tó bẹ́ẹ̀, mo bẹ Ọlọrun kó gba ẹ̀mí mi - Adekunle Gold

Àìsàn 'sickle cell' bá mi fínra tó bẹ́ẹ̀, mo bẹ Ọlọrun kó gba ẹ̀mí mi - Adekunle Gold

Ọjọ́ Ẹtì, 19 Oṣù Òkúdu 2026 ní 10:16:43

Adekunle bu ẹni atẹ lu bi awọn eeyan ṣe maa n kaanu awọn to n ba aisan naa finra ti wọn si maa n ro pe wọn ti gba ọjọ iku wọn.

A ti bẹ̀rẹ̀ sí ni lo ẹ̀rọ ‘Drone’ fi maa ṣe ìwádìí àti dẹkun ìwà ọdaran nipinlẹ Eko-Ọlọ́pàá

A ti bẹ̀rẹ̀ sí ni lo ẹ̀rọ 'Drone' fi maa ṣe ìwádìí àti dẹkun ìwà ọdaran nipinlẹ Eko-Ọlọ́pàá

Ọjọ́ Ẹtì, 19 Oṣù Òkúdu 2026 ní 10:05:35

Kọmiṣọna ọlọpaa ipinlẹ Eko, CP Tijani Fatai, funra rẹ ṣabẹwo si ọgba ile ẹkọ naa lana Ọjọru lati mọ nnkan to n ṣẹlẹ nibẹ.

Ijọba South Africa dínà mọ́ ìwé ìdánimọ̀ àwọn àjòjì tó ti dí ọmọ onílùú kan pa

Ijọba South Africa dínà mọ́ ìwé ìdánimọ̀ àwọn àjòjì tó ti dí ọmọ onílùú kan pa

Ọjọ́ Ẹtì, 19 Oṣù Òkúdu 2026 ní 10:00:22

Orilẹede naa ti di ibi ibẹru fun ọpọ eeyan to n gbe nibẹ lai jẹ pe ọmọ oniluu ni wọn.

A ti mú afurasí ọ̀daràn tó gé orí ọmọ ni Idanre, ìwádìí ti bẹ̀rẹ̀- Ọlọpaa Ondo

A ti mú afurasí ọ̀daràn tó gé orí ọmọ ni Idanre, ìwádìí ti bẹ̀rẹ̀- Ọlọpaa Ondo

Ọjọ́ Ẹtì, 19 Oṣù Òkúdu 2026 ní 08:30:51

Baba ọmọdebinrin naa, ọgbẹni Bright Kalu sọ pe iṣẹlẹ yi waye ni aba oko Agọti niluu Idanre lọjọ Aje, ọjọ karundinlogun, oṣu Kẹfa 2026 ọdun yi.

Ìgboro dàrú n’Ilorin lẹ́yìn ìròyìn tó tàn kálẹ̀ pé àwọn agbébọn ti ya wọ àwọn ilé ẹ̀kọ́, ọlọ́pàá kìlọ̀

Ìgboro dàrú n'Ilorin lẹ́yìn ìròyìn tó tàn kálẹ̀ pé àwọn agbébọn ti ya wọ àwọn ilé ẹ̀kọ́, ọlọ́pàá kìlọ̀

Ọjọ́bọ, 18 Oṣù Òkúdu 2026 ní 16:57:34

Eyi lo fa Ibẹrubojo kaakiri ilu Ilorin ti ọpọ obi ati alagbatọ si n sare kaba kaba lọ mawọn ọmọ wọn nile ẹkọ.

“Ọlọ́run kò dàbí ènìyàn,” mínísítà fún epo rọ̀bì tẹ́lẹ̀ sọ̀rọ̀ sókè lẹ́yìn tí ilé ẹjọ́ ní kò jẹ̀bi ẹ̀sùn rìbá gbígbà tí wọ́n fi kàn án

"Ọlọ́run kò dàbí ènìyàn," mínísítà fún epo rọ̀bì tẹ́lẹ̀ sọ̀rọ̀ sókè lẹ́yìn tí ilé ẹjọ́ ní kò jẹ̀bi ẹ̀sùn rìbá gbígbà tí wọ́n fi kàn án

Ọjọ́bọ, 18 Oṣù Òkúdu 2026 ní 18:55:52

L’Ọjọru ọsẹ yii ni ile ẹjọ UK kan gbe idajọ kalẹ wi pe Diezani ko jẹbi ọkankan ninu ẹsun onikoko mẹfa to da lori riba gbigba ti wọn fi kan an.

“Adedibu ò kú o, a sì ń rí Baálẹ̀ Molete”

"Adedibu ò kú o, a sì ń rí Baálẹ̀ Molete"

Ọjọ́bọ, 18 Oṣù Òkúdu 2026 ní 08:28:43

Ọrọ yii jade nigba ti Alhaja Modinat n sọrọ nibi ayẹyẹ iranti ọdun mejidinlogun ti Oloye Lamidi Ariyibi Adedibu jade laye.

Òní ni ìdájọ́ àwọn afurasí agbésùnmọ̀mí tó lé ní 400 yóò wáyé l’Abuja

Òní ni ìdájọ́ àwọn afurasí agbésùnmọ̀mí tó lé ní 400 yóò wáyé l'Abuja

Ọjọ́bọ, 18 Oṣù Òkúdu 2026 ní 08:23:02

Lara awọn ẹsun ti ijọba apapọ fi kan awọn eeyan naa ni kikopa ninu igbesunmọmi, nina owo sinu owo igbesunmọ, ṣiṣe iranwọ fun awọn agbesunmọmi, ati bẹẹ bẹẹ lọ.

Ìjọba Equatorial Guinea kọ̀wé fipò sílẹ̀ lẹ́yìn tó kùnà láti mú ìlérí rẹ̀ ṣẹ

Ìjọba Equatorial Guinea kọ̀wé fipò sílẹ̀ lẹ́yìn tó kùnà láti mú ìlérí rẹ̀ ṣẹ

Ọjọ́bọ, 18 Oṣù Òkúdu 2026 ní 05:15:16

Igbakeji Aarẹ orilẹede naa, Teodoro Nguema Obiang Mangue, lo fi idi ọrọ yii mulẹ.

Inú gbogbo èèyàn ìpínlẹ̀ Osun ló dún sí ìdájọ́ tó fààyè gba Accord láti díje, Adeleke ní wọ́n ń fẹ́ - Ìjọba Osun

Inú gbogbo èèyàn ìpínlẹ̀ Osun ló dún sí ìdájọ́ tó fààyè gba Accord láti díje, Adeleke ní wọ́n ń fẹ́ - Ìjọba Osun

Ọjọ́rú, 17 Oṣù Òkúdu 2026 ní 14:39:01

Agbẹnusọ fun Gomina Ademola Adeleke, Olawale Rasheed to ba BBC News Yoruba sọrọ lori idajọ naa sọ pe ki i ṣe gomina nikan ni idajọ ọhun dun mọ, bi ko ṣe gbogbo ọmọ ipinlẹ Osun pata.

Inú ìbànújẹ ọkàn ni mo wà torí àwọn ọmọdé wà ninu awọn èèyàn tawon janduku agbébọn ji gbe, bẹẹ, o ti le ni oṣu kan bayii- Makinde

Inú ìbànújẹ ọkàn ni mo wà torí àwọn ọmọdé wà ninu awọn èèyàn tawon janduku agbébọn ji gbe, bẹẹ, o ti le ni oṣu kan bayii- Makinde

Ọjọ́rú, 17 Oṣù Òkúdu 2026 ní 10:56:43

Makinde sọrọ yii lasiko ti alẹ́nulọ́rọ̀ ori ayélujára, Very Dark Man, at’awọn ọdọ mii n ṣèwọ́de niluu Ibadan lati pe fún ìtúsílẹ̀ àwọn akẹ́kọ̀ọ́ ti wọn ji gbe ọhun.

Àdó olóró agbésùnmọ̀mí ṣekúpa ọlọ́pàá mẹ́ta

Àdó olóró agbésùnmọ̀mí ṣekúpa ọlọ́pàá mẹ́ta

Ọjọ́rú, 17 Oṣù Òkúdu 2026 ní 07:21:37

Orukọ awọn agbofinro to padanu ẹmi naa bi ijọba ipinlẹ Zamfara ṣe kede ni: Abdulrazak Musa Hassan, Auwal Ahmad ati Murtala Musa.

Kí ló pa Oriyomi pọ̀ pẹ̀lú Surii Ilupeju, afurasí adigunjalè tí ọlọ́pàá ń wá? Ohun tí a mọ̀ rèé

Kí ló pa Oriyomi pọ̀ pẹ̀lú Surii Ilupeju, afurasí adigunjalè tí ọlọ́pàá ń wá? Ohun tí a mọ̀ rèé

Ọjọ́ Ajé, 15 Oṣù Òkúdu 2026 ní 08:11:14

Oriyomi ṣalaye ninu atẹjade kan to fi sita wi pe awọn ti wọn loun ni ibaṣepọ pẹlu Surajudeed fẹ ṣakoba fun ipolongo ibo oun ni.

Ṣé lóòótọ́ làwọn agbésùnmọ̀mí Lukarawa láti Apá Àríwá ti wọ inú igbó lọ l’Ogbomoso? Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá Oyo ti sọ̀rọ̀

Ṣé lóòótọ́ làwọn agbésùnmọ̀mí Lukarawa láti Apá Àríwá ti wọ inú igbó lọ l'Ogbomoso? Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá Oyo ti sọ̀rọ̀

Ọjọ́ Ajé, 15 Oṣù Òkúdu 2026 ní 15:44:18

Ileeṣẹ ọlọpaa Oyo sọ ninu atẹjade kan to fi sita loju opo X rẹ wi pe fidio naa ati ohun to wa nibẹ ko lẹsẹ nlẹ rara.

Iléeṣẹ́ ọmogun dóòlà ìyàwó ọ̀gágunfẹ̀yìntì tó kú sí àkàtà àwọn jàndùkú agbébọn lẹ́yìn tí wọ́n sin ọkọ rẹ̀

Iléeṣẹ́ ọmogun dóòlà ìyàwó ọ̀gágunfẹ̀yìntì tó kú sí àkàtà àwọn jàndùkú agbébọn lẹ́yìn tí wọ́n sin ọkọ rẹ̀

Ọjọ́ Ajé, 15 Oṣù Òkúdu 2026 ní 08:51:29

Alukoro fun ileeṣẹ ọmogun Naijiria, Ọgagun Samaila Uba, lo fọrọ yii lede lalẹ ọjọ Aje ọjọ kẹẹdogun oṣu Kẹfa yii.

Ṣé lóòótọ́ ni Kọmíṣọ́nà ọlọ́pàá Osun ń hùwà kò kàn mí sí rògbòdìyàn òṣèlú àti ètò ààbò tó mẹ́hẹ ní ìpínlẹ̀ náà? Ohun tí a mọ̀ rèé

Ṣé lóòótọ́ ni Kọmíṣọ́nà ọlọ́pàá Osun ń hùwà kò kàn mí sí rògbòdìyàn òṣèlú àti ètò ààbò tó mẹ́hẹ ní ìpínlẹ̀ náà? Ohun tí a mọ̀ rèé

Ọjọ́ Ìsẹ́gun, 16 Oṣù Òkúdu 2026 ní 07:00:34

Awọn ọdọ to ṣe iwọde l’Osogbo sọ pe bi Ọga Ọlọpaa ipinlẹ Osun, Ibrahim Gotan, ṣe dakẹ si gbogbo rogbodiyan n to ṣẹlẹ ni ipinlẹ Osun lasiko yii ku diẹ kaato.

Kí ló dé tí ẹnu ń kun Bàbá Ijesha lẹ́yìn tó kéde ọmọ tuntun?

Kí ló dé tí ẹnu ń kun Bàbá Ijesha lẹ́yìn tó kéde ọmọ tuntun?

Ọjọ́ Ìsẹ́gun, 16 Oṣù Òkúdu 2026 ní 11:21:05

Ninu fidio kan ti Baba Ijesha fi soju opo Instagram rẹ lo ti kede iroyin pe oun ati iyawo oun, Ceoluminee ti bi ọmọkunrin to pe orukọ rẹ ni King Kagar.

Hijrah: Kí ni pàtàkì ọdún tuntun yìí fún àwọn mùsùlùmí?

Hijrah: Kí ni pàtàkì ọdún tuntun yìí fún àwọn mùsùlùmí?

Ọjọ́ Ìsẹ́gun, 16 Oṣù Òkúdu 2026 ní 09:28:01

Iyatọ to wa laarin ọdun musulumi ati ọdun yooku ni pe wọn ko kii ṣe e papọ pẹlu awọn yooku ati pe orukọ wọn yatọ.

Kò sí ogun mọ́, kò sí ọ̀tẹ̀ mọ́! Amẹ́ríkà àti Iran fẹnukò láti fòpin sí ogun àárín wọn

Kò sí ogun mọ́, kò sí ọ̀tẹ̀ mọ́! Amẹ́ríkà àti Iran fẹnukò láti fòpin sí ogun àárín wọn

Ọjọ́ Ajé, 15 Oṣù Òkúdu 2026 ní 13:32:41

Olootu ijọba orilẹede Pakistan, Shehbaz Sharif, to jẹ alarena laarin orilẹede mejeji lo fi ọrọ naa lede lalẹ ọjọ Aiku.

Ọmọsẹ́ gbẹ̀mí ọ̀gá rẹ̀ ní Kwara, ó tún ń bèrè ₦2m lọ́wọ́ ẹbí olóògbé

Ọmọsẹ́ gbẹ̀mí ọ̀gá rẹ̀ ní Kwara, ó tún ń bèrè ₦2m lọ́wọ́ ẹbí olóògbé

Ọjọ́ Ajé, 15 Oṣù Òkúdu 2026 ní 12:46:46

Ọga agba ajọ NSCDC, Abbas Nda Mohammed lo fi ọrọ naa lede lọjọ Aiku, ọjọ kẹrinla, osu Kẹfa, ọdun 2026 ti a wa yii ni olu ileesẹ ajọ naa lẹyin iwadii lori bi oloogbe ọhun ṣe dede dawati.

Àjọ CAN kéde ọjọ́ òní gẹ́gẹ́ bíi ọjọ́ ‘Àìkú Dúdú’ láti dárò àwọn ọmọ Naijiria tó ń jìyà ètò ààbò tó mẹ́hẹ

Àjọ CAN kéde ọjọ́ òní gẹ́gẹ́ bíi ọjọ́ 'Àìkú Dúdú' láti dárò àwọn ọmọ Naijiria tó ń jìyà ètò ààbò tó mẹ́hẹ

Ọjọ́ Àìkú, 14 Oṣù Òkúdu 2026 ní 14:09:32

CAN kede ọrọ naa ninu iṣẹ ti Aarẹ wọn, Archbishop Daniel Okoh, ran si gbogbo Kristẹni lonii ọjọ Aiku, ọjọ kẹrinla, oṣu Kẹfa ọdun 2026.

Ìtàn Mánigbàgbé: Ìdí tí Ọba alayé nílẹ̀ Yorùbá kìí ṣe dúró níbi tí wọn ti ń pa èèyàn tàbí fojú rí òkú

Ìtàn Mánigbàgbé: Ìdí tí Ọba alayé nílẹ̀ Yorùbá kìí ṣe dúró níbi tí wọn ti ń pa èèyàn tàbí fojú rí òkú

Ọjọ́ Àìkú, 14 Oṣù Òkúdu 2026 ní 06:44:50

BBC News Yorùbá wọnú ìtàn lọ nípa ìdí tí Ọba alayé nílẹ̀ Yorùbá kìí ṣe dúró níbi tí wọn ti ń pa èèyàn tàbí fojú rí òkú.